Ọjà Enugu dahoro tórí ókú ọ̀pọ̀ ẹyẹ igún tó balẹ̀

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Awọn oku ẹyẹ igunugun ti wọn ri kaakiri ilẹ lọja Eke-Ihe ni ijọba ibilẹ Awgu ti di ọrọ to n tan kalẹ laarin awọn araalu latari fidio kan to wa lori ẹrọ ayelujara lati ọjọ aiku.
Iroyin to tẹle eyi ni wi pe lẹyin ti wọn jẹ ẹran maalu ni awọn ẹyẹ igun naa fo ṣanlẹ ku.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
Ẹwẹ, agbẹnusọ fun ile iṣẹ Ọlọpaa, Ebere Amaraizu ti wa fi ọrọ ranṣẹ fun awọn araalu pe ki wọn ma foya o.
Ile iṣẹ Ọlọpaa ipinlẹ Enugu bu ẹnu atẹ lu ọpọlọpọ ẹsun to n tan kalẹ ati eyi to sọ pe iṣẹ ọwọ awọn to n ji ẹranko pa lọna aitọ lo fa iku awọn ẹranko abiyẹ naa.
O ni ṣe ni awọn to ma n pa wọn yii ma n po nkan pọ mọ ẹran ti wọn ti pa silẹ ati igbẹ wọn lati fa oju awọn Igunugun mọra ki wọn lee wa jẹ.
Wọn ni bi wọn ba ti jẹ ẹ, ara a rẹ wọn, wọn a si gba ibẹ ku ki awọn to ji wọn pa le lọ ko wọn.
Ẹwẹ, iroyin naa sọ pe awọn ẹyẹ Igun kan to ko si panpẹ apopọ yii ja bọ si ọja ilu Enugu, awọn to maa n ko wọn ko si tete ri wọn ko kọ̀rọ̀ naa to di tọrọ̀ fọn kalẹ.
Ni ile iṣẹ Ọlopaa jẹ ko di mimọ pe iku wọn ko wa latọwọ ẹran kankan ti wọn pa fun jijẹ awọn eniyan bi ko ṣe iṣẹ ọwọ awọn ẹni ibi to fẹ da omi alafia ilu ru ni.
Kọmisana ni ki wọn ma jẹ ko di wọn lọwọ iṣẹ oojọ wọn ki wọn si jẹ araalu to n pa ofin mọ tori awọn ṣi n ṣe iwadii boya ẹran maalu kan ti wọn pa ti wọn si n ta lọja Eke-Ihe lo fa iku wọn.
Awọn Iroyin mii ti ẹ le nifẹ si
- Barrister ló sọ mí di èèyàn ńlá - Ayinla Kollington
- Ìtàn tó wà nídi òwe ‘Sebótimọ Ẹlẹ́wà Sàpọ́n’
- Ìtàn tó rọ̀ mọ́ òwe ‘aṣọ kò bá Ọ́mọ́yẹ mọ́...’ rèé
- Afọnja, ẹni tó finú wénú ní Ilọrin, àmọ́ tó jẹ iwọ
- Ẹfunsetan Aniwura, obìnrin tó ju ọkùnrin lọ
- Ọ̀rọ̀ǹpọ̀tọ̀niyùn, Aláàfin obìnrin àkọ́kọ́ rèé, tó ní nǹkan ọkùnrin













