Ọba ìlú Epe Ekiti fi àṣẹ ìṣẹ̀mbáyé ṣépé fáwọn ọmọ ìlú, ìlú bá fárígá fìbínú lé nílùú
Awọn ara ilu Epe-Ekiti ni ijoba ibile Ijero ni ipinlẹ Ekiti ti ke si ijoba Ekiti lati bawọn fi aṣẹ si igbesọ ti wọn gbe lati rọ Ọba wọn Ayọdeji Williams Adesoye lóye.
Ṣaaju ni awọn ọmọ ilu Epe Ekiti ti fi ẹsun oriṣiriṣi kan Ọba Ayọdeji nipa aṣilo ipo rẹ lori itẹ awọn babanla rẹ.
Wọn si fariga pe eewọ nla ni iru iwa yii nilẹ Yoruba, ti wọn si taku pe lilọ ni oriade naa yoo lọ kuro ninu ilu naa fun awọn tori oriṣiriṣi ajalu ibi ti o le ti ẹyin rẹ yọ.
Ninu ọrọ rẹ pẹlu Akọroyin BBC News Yoruba, Oloye agba Olajide Dada, ti o jẹ igbakeji Ọba ati Olori awọn Afọbajẹ ni ilu Epe-Ekiti ṣalaye orisirisi awọn iwa ẹgbin tí oríadé náà hu bii fifi aṣẹ ilu ṣepe fun awọn Ọmọ ìlú.
O ni awọn araalu lo taku pẹlu ifẹhonuhan pe ki ìjọba ipinle Ekiti rọ Ọba Ayọdeji loye, ki ilu Epe-Ekiti ma ba a tuka.



