Sunday Igboho: Ẹ gbọ́ ohun tí Sanwo-Olu sọ lórí ọ̀rọ̀ Sunday Igboho

Gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu ti sọrọ lori ohun tawọn gomina ilẹ Yoruba n ṣe lori bi wọn ju Oloye Sunday Adeyemo(Igboho) si atimọle ni ilu Cotonou, lorilẹede Benin.

Ọpọ eeyan lo ti n kọminu pe awọn gomina apa iwọ oorun guusu ko sọ ohun kan loi bi wọn ṣe mu Igboho lorilẹede Benin.

Gomina Sanwo-Olu sọ fawọn akọroyin nibi eto idibo ijọba ibilẹ Eko lọjọ Abamẹta pe iṣẹ n lọ labẹlẹ lori ọrọ Igboho.

''Awọn eeyan n ṣiṣẹ lọ labẹlẹ, ko digba tawọn gomina ba to n sọrọ ni gbangba ki araalu to mọ pe wọn o dakẹ lori ọrọ Igboho.

Asiko yii to le ni akoko yii fun gbogbo wa, ṣugbọn mo fẹ fi da yin loju pe iṣẹ n lọ labẹlẹ.

Nibi ti ọrọ de duro bayii, ko niṣe pẹlu iye awọn akọroyin ti eeyan ba ba sọrọ.

Ohun ti mo mọ ni pe ọpọ eeyan lo n ṣiṣẹ lẹgbẹ lẹgbẹ ati lọlọdanni, ko digba ti wọn ba to sọrọ ni gbangba,'' Sanwo-Olu ṣalaye.

Ọjọ Aje ọjọ kọkandinlogun oṣu keje lawọn agbofinro mu Igboho ni papakọ ofurufu Cadjèhoun niluu Cotonou, lorilẹede Benin.

Oun ati iyawo rẹ, Ropo ni wọn n jọ n rinrin ajo lọ si orilẹede Germany nibi ti wọn ti fẹ wọ baalu laago mẹjọ alẹ ki wọn to mu wọn.

Ṣugbọn awọn gomina ilẹ Yoruba ko ti sọrọ lori iṣẹlẹ ọhun lati ọjọ Aje ti Igboho ti wa ni gbaga ọlọpaa.

Ohun ti ijọba orilẹede Naijiria sọ fun Benin ni pe Igboho ti lu ofin ni Naijiria wi pe ki wọn mu un nibẹ.

Awọn aṣoju ijọba Naijiria tun sọ fun ile ẹjọ ni Benin pe Igboho ko ibọn pamọ sile eleyii ti o fẹ lo lati pin orilẹede Naijiria.

Wọn tun sọ pe Igboho n lo awọn eeyan lati da ilu ru.

Ijọba Naijiria tun sọ pe Igboho n ṣe fayawọ ibọn.

Ṣugbọn ọkan lara awọn agbẹjọro Igboho, Ibrahim Salami to ba BBC Yoruba sọrọ ṣalaye pe ko si otitọ kankan ninu awọn naa.