Travelogue on Abeokuta: Ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀dógún yònbó ìbùdó àti èèyàn pàtàkí tó wà ní Abeokuta
Yoruba ni ọmọ ti yoo ba jẹ Asamu, kekere ni yoo ti maa jẹnu samusamu.
Asamu ọmọ si la le pe Grace nitori bo se n jẹnu samusamu lati yonbo ilu abinibi rẹ, Abeokuta, to si salaye yekeyeke nipa awọn ibudo pataki to wa nilu naa.
Lara awọn ibi manigbagbe ti Grace mẹnuba ni Apata Olumo, Aafin Alake tilẹ Egba, Gbọngan ti wọn fi sami ọgọrun ọdun ti wọn tẹ Abeokuta do ati ile ijọsin onigbagbọ akọkọ to wa nilu naa.
Bakan naa ni Grace, tii se ọmọ ọdun mẹẹdogun, tun sọ awọn ibudo igbafẹ atawọn eeyan pataki to jẹ ọmọ bibi ilu Abeokuta.
- Ẹ wo ìbejì ológo tó bẹ̀rẹ̀ orin kíkọ̀ ní ọmọ ọdún mẹ́ta
- Wo ohun mẹ́wàá tó yẹ kóo mọ̀ nípá ọmọ ọdún mẹ́wàá Emmanuella tó kọ́ ilé ńlá fún ìyá rẹ̀
- Adesoji Aderemi, Ọọ̀ni Ifẹ̀ àti gómìnà Adúláwọ̀ àkọ́kọ́ láyé eèbó amúnisìn
- N kò kàwé rí nílé ìkàwé àmọ́ èmi ni akẹ́kọ̀ọ́ tó pegedé jùlọ ní fásitì LASU - Sotunde
Ko tan sibẹ, ọmọde yii tun sọ nipa itan bi wọn se da ilu naa silẹ ati awọn eeyan jankanjankan to ti se ribiribi fun agbaye, ti wọn jẹ ọmọ bibi ilu Abeokuta.
Lara awọn to mẹnuba ni Ọjọgbọn Wole Soyinka, Oloye Olusegun Obasanjo, Fela Anikulapo Kuti, Oloye MKO Abiola, Ernest Sonekan ati bẹẹ bẹẹ lọ.
Grace wa ke sawọn onile ati alejo pẹlu awọn eeyan lagbaye to n wa ibi igbafẹ ti wọn fẹ lọ, paapaa awọn ọdọ lati wa silu Abeokuta.
Koda, o fikun pe wọn yoo ge ahọn jẹ ti wọn ba fi ẹnu kan irẹsi Ọfada ati amala Lafun, tii se ounjẹ ibilẹ wọn nilu Abeokuta.
Itan aye awọn ọmọ bibi ilu Abeokuta to laami laaka ni agbaye:
- MKO Abiola, iṣẹ́ aṣẹ́gità ló fi bẹ̀rẹ̀ okoòwò
- Ayinla Ọmọwura, orin èébú àti oríyìn lo fi di ọ̀rẹ́ àwọ̀n obìnrin
- Ṣo mọ̀ pé J.F Odunjo jẹ aṣòfin àti mínísítà nílẹ̀ yìí, yàtọ̀ sí pé ó jẹ́ òǹkọ̀wé?
- Lisabi Agbongbo Akala rèé, ẹni tó fi ìfẹ́, ìṣọ̀kan àti ìrẹ́pọ̀ gba ilẹ̀ Ẹ̀gbá lọ́wọ́ ìmúnisìn
- Kíni ìwọ mọ̀ nípa Funmilayọ Ransome-Kuti?
- Hubert Ogunde rèé, baba àwọn òsèré tíátà
- Ẹfunroye Tinubu - Ògbóǹtagí oníṣòwò, olówò ẹrú àti afọbajẹ
- Ọbasanjọ sọ àsírí sàgbàdèwe rẹ̀



