You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Baba Ijesha: Àkójọpọ̀ ìwádìí wa rèé nípa gbígbá béèlì Olanrewaju Omiyinka
Oju opo ayelujara ati tawọn ileeṣẹ iroyin Naijiria kan n gbona janin-janin lọsan ọjọ Aje, lori iroyin kan pe Baba Ijesa to wa ni ahamọ ọlọpaa ti gba itusilẹ.
Lati nkan irọlẹ ọjọ Aiku ni iroyin yii ti kọkọ lu jade sigboro, ti awọn eeyan si n gba bi ẹni gba igba ọti kaakiri.
Idi si niyi ti BBC Yoruba fi n se iwadi pe se lootọ ni wọn ti gba oniduro Olanrewaju James, ti gbogbo eeyan mọ si Baba Ijesa, tabi o si wa ni ahamọ ọlọpaa?
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
- Ẹ̀sùn gbígbìyànjú láti wọ́lé sí ojú ara ọmọdé pẹ̀lú ìpá àtàwọn ẹ̀sùn mìí tí Baba Ijesha yóò jẹ́ rèé
- Ẹ fi Baba Ijesha sílẹ̀ fún mi, màá ṣe onídùróó rẹ̀ - Yomi Fabiyi
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
- Ẹ̀yin tí Baba Ijesha bá ọmọ tàbí àbúrò yín lòpọ̀ láìtọ́, ẹ fi ẹjọ́ ṣùn mí - Princess Comedian
- Davido sí Yomi Fabiyi: Mùmú ni ẹ́
- Màá pe Kọ̀mísánà ọlọ́pàá Eko àti igbákejì rẹ̀ lẹ́jọ́ lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha - Amofin
- Aá ṣe ìwọ́de tako ọlọ́pàá láàrin ọjọ́ méje lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha - Yomi Fabiyi
Ọna lati ri okodoro ọrọ nipa ahesọ ọrọ yii lo mu wa pe awọn to sunmọ Baba Ijesa ati awọn agbofinro to fi si ahamọ lori ẹsun aṣemase pẹlu ọmọdebinrin kan.
Yomi Fabiyi - N ko gbọ pe wọn ti gba beeli Baba Ijesha
Ninu awọn to lewaju pe ki wọn tu Baba Ijesa silẹ ni gbajugbaja osere Yomi Fabiyi wa.
Ninu ijagudu rẹ fun idande Baba Ijesha ni ahamọ, Fabiyi ni ofin lo yẹ ka tẹle lori ọrọ Baba Ijesa nitori naa, ko yẹ ki o wa ni ahamọ gbere titi ti wọn yoo fi gbẹjọ rẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Mò ń wá olè tó jí nńkan ní ọọ́físì mi, ẹ̀bùn owó iyebíye rèé - Afeez Eniola
- Ẹ̀yin Gómìnà, ọwọ́ yín ni ọ̀nà àbáyọ sí ìṣòro Nàíjíríà wà - Atiku
- Àwọn gómìnà ẹgbẹ́ PDP wọ̀lú Ibadan fún ìpàdé
- Ẹ fi Baba Ijesha sílẹ̀ fún mi, màá ṣe onídùróó rẹ̀ - Yomi Fabiyi
- Àgbà ọ̀jẹ̀ akọrin Fuji, Amoo Igisekele, jáde láyé
- Òkùnkùn birimùbirimù ni Kaduna bi àwọn òṣisẹ ṣe gùn le ìyànṣẹ́lódì-wo bi yóò ṣe kan ìwọ naa
- Wo ìdí méje tí olólùfẹ́ rẹ fi le kọ ìbálòpọ̀ pẹ̀lú rẹ
- Digbí ni ojú irin Kaduna- Abuja wà - Ọlọ́pàá Kaduna
- Ojú mi rí màbo nígbà tí mo bímọ àkọ́bí, ẹ̀ṣẹ̀ ni ká bímọ láì rí owó tọ́jú rẹ̀ - Lizzy Anjorin
Amọ nigba ti BBC Yoruba kan si lori aago rẹ, Fabiyi ni oun ko ti gbọ pe wọn ti gba beeli Baba Ijesa.
O ni ''Bi o ba jẹ pe wọn gba beeli rẹ, ohun to yẹ labẹ ofin naa lo ṣẹlẹ yẹn''
O ni bi awọn eeyan ṣe n gbọ pe wọn tu silẹ loun naa ṣe n gbọ ṣugbọn bi oun ba ri aridaju ọrọ yii, oun yoo fi to wa leti.
Alukoro ileeṣẹ Ọlọpaa - N ko gbọ rara pe wọn ti gba beeli Baba Ijesha
Esi Yomi Fabiyi yii si lo mu wa kan si alukoro fun ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Eko lati fidi ootọ ọrọ naa mulẹ.
Nigba to n fesi pada lori atẹjisẹ ta fi ransẹ si, Muyiwa Adejobi tii se Alukoro ọlọpaa ipinlẹ Eko ni oun ko mọ rara boya wọn ti tu afurasi naa silẹ ni ahamọ ọlọpaa.
Amọ sibẹ isẹju- isẹju ni awọn iroyin n kan wa lori ayelujara pe wọn ti gba beeli Baba Ijesha, ti a ko si ri aworan, fidio tabi ẹnikẹni to fidi ọrọ naa mulẹ.
Koda, awọn ololufẹ wa loju opo Facebook BBC Yoruba gan n sọ pe awọn hu gbọ nipa pe wọn ti gba beeli Baba Ijesha sugbọn a ko ri aridaju kankan nipa rẹ.
Niwọn igba ti ileesẹ ti wa kii he ira ti ko mi ọmọ ninu, to ba se jẹ, iwadi si n tẹ siwaju, a maa kan si yin.