You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Zamfara abduction: Ìjọba ìpínlẹ̀ Zamfara ní irọ́ ni ìròyìn tó sọ pé àwọn ti rí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ náà padà
Ijọba ipinlẹ Zamafara ti kede pe awọn agbebọn to ji awọn akẹkọọbinrin ile ẹkọ Government Girls Science Secondary School, Jangebe, gbe ko tii tu awọn akẹkọọ naa silẹ.
Ṣaaju ni iroyin kan ti kọkọ gbode lọsan ọjọ Aiku pe wọn ti tu awọn ọdọbinrin naa silẹ, ati pe wọn ti wa ni ikawọ ijọba.
Ninu atẹjade kan ti agbẹnusọ gomina Bello Muhammad Matawalle, Jamilu Ilyasu Magaji fi sọwọ si BBC, o ni irọ nla gbaa ni iroyin naa.
- Ẹ wo àwòrán bí Sunday Igboho ṣe ṣàbẹ̀wò sí Aarẹ Gani Adams nílé rẹ̀ nílùú Eko
- Èèyàn méje móríbọ́ lẹ́yìn tí àwọn ajínigbé àtàwọn ọdẹ ìlú rọ òjò ìbọn fún ara wọn l'Ondo
- Wọ ohun tí a mọ̀ nípa gbajúgbajù olórin ọmọ Naijiria, Dr Frabz tí wọ́n yìnbọn pa ?
- Ọjọ́ Ìṣẹ́gun ní abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 tó tó 4 milionu yóò bàlẹ̀ sí Nàìjíríà
Irọ́ ni o! A kò tíì rí àwọn akẹ́kọ̀ọ́bìnrin tó lé ní 300 tí wọ́n jí gbé ní GGSS Jangebe - Ìjọba Zamfara
Magaji ni "lati ọjọ Ẹti ti wọn ti ji awọn akẹkọọ naa gbe, gomina ati gbogbo awọn alabaṣiṣẹ rẹ ko tii sinmi nitori akitiyan lati wa awọn akẹkọọ naa ri."
"O ṣeni laanu pe awọn kan ti ko mọ ohun to n lọ le lọ gbe iroyin jade pe a ti ṣawari awọn akẹkọọ naa."
- Sunday Igboho gbọdọ̀ gbàṣẹ ìdáàbòbò láti iléẹjọ́ tí kò ní jẹ́ kí ọlọ́páá mú un- Amòfin Ozekhome
- Fáàbàdà! Ìjọba mi kọ́ ní yóò buwọ́lu ìgbéyàwó akọ sákọ àti abo sábo- Ààrẹ Ghana yarí
- Àwọn jàndùkú ajínigbé fẹ́ẹ̀ lù wá pa nínú igbó, ọ̀rọ̀ rèé lẹ́nu àwọn àkẹ́kọ̀ọ́ ìlú Kagara
- Ẹ wo ohun tí a mọ̀ nípa Dawisu tí gómínà Kano yọ ní íṣẹ́ nítorí o sọ̀rọ̀ tako Ààrẹ Buhari
Magaji sọ pe irufẹ iroyin ti ko ni gbongbo bayii le ṣakoba fun akitiyan awọn ẹṣọ alabo to n wa awọn ọmọ naa, ati pe o le mu ibanujẹ ọkan ba awọn obi awọn akẹkọọ ọhun.
O pari atẹjade naa pe ijọba ipinlẹ Zamfara yoo bun awọn ọmọ Naijiria gbọ ni kete ti wọn ba ti ṣawari awọn akẹkọọ ọhun.
- Mi ò gba kobo ní gbogbo ọ́dún mẹ́jọ mi gẹ́gẹ́ bíi gómìnà ìpínlẹ̀ Osun - Aregbesola
- Wọ́n ní ọkọ̀ bàálù NAF tó mú ẹ̀mí ọmọ mi lọ l'Abuja ti lo ọdún 49 láyé - Bàbá Flight Sergent Olasunkanmi
- Wo àwọn ìlú tó jẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti èèwọ̀ ni kí ènìyàn kú níbẹ̀
- ''Pásítọ̀ ní kí n gbé ọwọ́ lé ǹkan ọkùnrin ọ̀un, ní ejò dúdú bá jádé...''
Agbébọn tún jí akẹ́kọ̀ọ́bìnrin 317 gbé ní Zamfara
Lalẹ ọjọ Ẹti, iroyin jade wipe akẹkọbinrin meje ninu awọn ọọdunrun o le mtadinlogun ti awọn ajinigbe ji gbe ti bọ mọ wọn lọwọ.
Awọn araalu ti ipadabọ wọn ṣoju wọn sọfun awọn oiroyin pe wọn ti pada sinu ilu wọn funrawọn gẹgẹ bi wọn ṣe ni awọn kan dede wa ọna awọn lati pada sile nigba ti wọn n rin kiri ninu igbo aginju ti awọn ajinigbe gbe wọn lọ.
Gẹgẹ bi oṣojumikoro naa ṣe sọ, o ni awọn ọmọ naa ni awọn mii naa ti sa ti wọn yoo si to pada sile.
Gomina Matawalle paṣẹ ki wọn gbe gbogbo ileewe oniyara akẹkọọ ti pa ni Zamfara
Lẹyin ti iroyin ijinigbe yii tan ka gbogbo agbaye ti awọn ajọ ati orilẹede agbaye si ti n da si i ti wọn ti n fi ọrọ ranṣẹ si Naijiria, gomina ipinlẹ Zamfara ti paṣẹ pe ki wọn gbe gbogbo ileewe oniyara akẹkọọ ti pa ni Zamfara.
Bakan naa ni ọlọpaa ipinlẹ naa ni awọn ti bẹrẹ igbesẹ lati ri aridaju idoola awọn akẹkọbinrin naa.
Ọlọpàá ní iye àwọn akẹ́kọ̀ọ́bìnrin GGSS Jangebe tí wọ́n jí gbé jẹ́ 317
Iroyin to ṣẹṣẹ n jade sita sọ pe awọn ajinigbepawo tun ti ṣọṣẹ ijinigbe ni ilu Jangebe ipinlẹ Zamfara.
Akẹkọọbinrin ni wọn tun ji gbe lọtẹ yii, wọn o si kere niye rara. Ṣaaju, iye ti wọn kọkọ sọ ni pe ọọdunrun ọmọbinrin ni wọn ti ji gbe.
Ko tii si aridaju kankan nipa awọn to ji awọn akẹkọ naa gbe bẹẹ si ni ko sẹni to mọ ibi ti wọn gbe wọn lọ.
Ẹwẹ, awọn ti ile iṣẹ iroyin BBC ba sọrọ sọ pe o daju wipe o le lọọdunrun awọn ọmọbinrin naa ti wọn jigbe nileewe ni Zamfara.
- Irọ́ ni pé wọ́n ti fi àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Kagara sílẹ̀- Gomina ìpínlẹ̀ Niger
- Àwọn jàndùkú ajínigbé kìí sáábà sekú pààyàn, owó ni wọ́n ń fẹ́- Sheikh Gumi
- Wo àsọdùn ìròyìn tíléeṣẹ́ ìròyìn òkèèrè gbé lórí ìṣẹ̀lẹ̀ ìjínigbé akẹ́kọ̀ọ́bìnrin Nàìjíríà
- Fayemi: Àfàìmọ̀ kí ìjọba má bá àwọn jàndùkù ajínigbé sọ̀rọ̀, àmọ́ onímọ̀ nípa ètò àbò ní ...
- Wọn ò fẹnu kò mi lẹ́nu rí tàbí lọ́ mọ́ mi lẹ́yìn ìtàgé, kí n tó di oní Hijab - Arapa re gangan
Baba ọkan lara awọn akẹkọ naa ati olukọ ni ileewe naa sọ fun BBC pe lootọ ni o ṣẹlẹ.
Oṣojumikoro sọ nigba ti wọ́n fi ka iye awọn ọmọ ile iwe naa to ku nilẹ ni wọn ri i pe irinwo lawọn ti wọn ko ri.
Ileeṣẹ iroyin News Agency of Nigeria naa royin rẹ pe Kọmisọna eto abo nibẹ, Abubakar Dauran sọ pe ọgọgọrun awọn ọmọ ileewe ni awọn agbebọn ti ji gbe l ṣugbn ti ko sọ iye wọn pato ni tirẹ.
Eyi waye ni ko pẹ ti akitiyan ṣi n lọ lọwọ lati doola awọn akẹkọọ Kangara ti wọn ṣẹṣẹ ji gbe lọsẹ to kọja.
Bawo lo ṣe ṣẹlẹ?
Kabiru Sani ti wọn ji aburo rẹ mẹta gbe sọ fun BBC pe awọn agbebọn naa yabo ileewe ọhun wọn si ko gbogbo awọn ẹṣọ alaabo ni papamọra ki wọn to ri awọn akẹkọọ naa gbe.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, "o ju ọọdunrun le aadọrin awọn obinrin ti wọn ji gbe ti awọn ọmọbinrin naa si wa lati ipinlẹ ọtọọtọ bii Kaduna, Sokoto, Kano, Jigawa ati Kebbi".
"Bi wọn ṣe de, wọn yi ileewe naa kaati gbogbo ibi ti wọn mọ pe awọn ẹṣọ alaabo wa wọn si kọlu ẹnu ibode ileewe, ẹṣ kan dide o si yinbọn amọ nigba to ri i pe agbara rẹ ju toun lọ, o sa lọ. Bi wọn ṣe rọna wọ yara awọn akẹkọbinrin naa ti wọn si n ji wọn ko.