You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Femi Fani-Kayode: Ọ̀rẹ́ lásán ni Halima Yusuf jẹ́ sí mi, kìí ṣe àfẹ́sọ́nà mi
Nnkan bi ọjọ diẹ sẹyin ni iroyin kan gbode lori ayelujara pe, Minisita tẹlẹ feto irina ọkọ ofurufu, Femi Fani-Kayode fẹ gbe iyawo tuntun.
Bẹẹ ba si gbagbe, ko tii ju bi osu kan lọ, ti iroyin gbalẹ lori ayelujara pe igbeyawo Fni-Kayode ati iyawo ile rẹ ti fori sanpọn.
Ṣugbọn minisita ọhun ti fọhun sita pe, irọ patapata ni iroyin naa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ifẹ́ Yorùbá ló mú mí fi ẹ̀mí mi wéwu láti koju ajínigbé ní Kishi - Sunday Igboho
- Ìbò 900m làwọn èèyàn di lórí ètò BBNaija tó ṣẹ̀ṣẹ̀ parí - MultiChoice
- €10,000, ara owó tí wọn fi ra Ighalo pòórá, Ilé aṣòfin Osun bẹ̀rẹ̀ ìwádìí
- Ìwádìí BBC rèé lórí ẹ̀sùn gbájuẹ̀ $120,000 tí wọ́n fí kàn igbákejì olórí òṣìṣẹ́ ìjọba l‘Osun
- PDP àti APC fi ìbọn dárà l'Ondo, ọ̀pọ̀ èèyan farapa, àìmọye dúkìá ṣòfò
- "Dípò ìnákúnàá lórí ìgbéyàwó ọmọ mi, mo lò owó fún ìgbéyàwó ọmọ òrukàn mẹ́tàlá"
- Àwàdà kẹríkẹrì nígbà táwọn olùdíje ààrẹ́ Amerika méjì kọjú ìjà síra wọn
- Ìjọba àpàpọ̀, jọ̀ọ́ máṣe yẹ̀ lórí àdéhùn rẹ fẹ́gbẹ́ òṣìṣẹ́ - Ile aṣojú-ṣòfin
- Ọgọ́rin arìnrìnàjò tó padà wá sí Nàìjíríà ló ní Coronavirus - PTF
O ni oun ko ṣetan lati gbe iyawo lasiko yii, obirin ti awọn eeyan n ṣọ pe oun fẹ gbe niyawo, Alima Yusuf, kii ṣe afẹsọna oun, bikoṣe ọrẹ lasan.
Fani-Kayode lo kede ọrọ naa ninu atẹjade kan to fi sita loju opo Instagram rẹ, nibi to ti parọwa si awọn eeyan lati dẹkun pinpin iroyin ofege nipa oun kiri lori ayelujara.
O ni "Awọn kan ti n gbe ahesọ kan kiri lori ayelujara pe mo n mura fun igbayawọ laipẹ, irọ ni o."
"Omidan Halima Yusuf, ti wọn n pe ni afẹsọna mi kii ṣe afẹsọna mi rara, ọrẹ lasan lo jẹ si mi, o si tun jẹ olufọkantan ati ẹni apọnle lọwọ mi."
Fani-Kayode ṣalaye pe obinirin naa, yatọ si awọn eeyan miran, jẹ olutunu fun oun lasiko yii, ati pe oun mọ riri rẹ ninu aye oun.
- Ìjọba àpàpọ̀, jọ̀ọ́ máṣe yẹ̀ lórí àdéhùn rẹ fẹ́gbẹ́ òṣìṣẹ́ - Ile aṣojú-ṣòfin
- Wo iye tí ìjọba yóò gbà lọ́wọ́ Laycon gẹ́gẹ́ bí owó orí ẹ̀bùn BBNaija tó jẹ
- Ilé ẹjọ́ gíga ní kí òsìsẹ́ First Bank tẹ́lẹ̀ lọ sí ẹ̀wọ̀n ọdún 98 lórí ẹ̀sùn pé o jí mílíọnù 49 àti $368, 000 níbẹ̀
- Àríyá yá! Sẹ́nátọ̀ Elisha Abbo kési Naira Marley láti ṣe àríyá fún Leycon tó borí ní BB Naija
Minisita naa pari ọrọ rẹ pẹlu ẹbẹ pe, ki gbogbo awọn gboyi-sọyi lọ so ewe agbejẹ mọwọ nitori oun ko ṣetan lati gbe obinrin naa niyawo.
Tani Halima Yusuf?
Ọmọ bibi ipinlẹ Bornu ni Halima, ṣugbọn ipinlẹ Gombe lo fi n ṣebugbe pẹlu awọn ẹbi rẹ, ko to tẹkọ leti lọ si ilu Abuja ni nnkan bi ọdun diẹ sẹyin lati bẹrẹ iṣẹ owo ṣiṣe.
Gẹgẹ bo ṣe sọ loju popo Instagram rẹ, Halima ni alaṣẹ ati oludari ileeṣẹ Sly Royal, nibi to ti n ta aṣọ awọn obinri ati awọn ẹṣọ ara.
Bakan naa lo tun ṣọ pe oun n ṣowo awọn ohun aṣara loge fun awọn obinrin.
Bo tilẹ jẹ pe o ṣoro lati sọ iye ọjọ ori rẹ, ati ileewe to lọ lasiko yii, ọpọ eeyan lo ti n woye pe, o yẹ ko sọrọ lori ibaṣepọ rẹ pẹlu Femi Fani-kayode.