Lebanon: Peace Busari àti àwọn 28 míràn ló padà sí Naijiria

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Arabinrin Peace Busari ti olowo rẹ lorilẹede Lebanon fẹ ta loju opo Facebook ti pada wale si Naijiria.

Alaga Ajọ Nigerians in Diaspora Commission, Abike Dabiri-Erewa, lo fi lede bẹẹ ni oju opo Twitter rẹ.

Abike Dabiri-Erewa ni arabinrin Peace Busari pada sile pẹlu awọn mọkandinlọgbọn miran ti wọn wa ni oko ẹru ni Lebanon naa.

O saleye pe ki wọn to pada si Naijiria, Busari wa pẹlu ikọ to n bojuto awọn ọmọ Naijiria to wa ni Beirut, Lebanon, lẹyin ti wọn gba pada lọwọ olowo rẹ.

Ọgbẹni Wael Jerro polowo Busari Peace pẹlu iwe irina rẹ ọmọ ipinlẹ Oyo loju opo Facebook rẹ ni oṣu diẹ ṣẹyin.

Eleyii lo bi awọn ọmọ Niajiria ninu ti wọn si pe fun itusilẹ Busari ati ki wọn fi panpẹ ọba mu Jerro to polowo rẹ lori ayelujara.

Lẹyin naa ni Dabiri-Erewa kede pe panpẹ ọba ti mu arakunrin naa ti awọn si ti bẹrẹ eto lati mu arabinrin Busari pada sile.

Ọkùnrin Lebanese tó lu ọmọ Nàìjíríà ní gbàǹjo lórí Facebook ti kó sí páńpẹ́ ọlọ́pàá

Ọmọ orilẹede Lebanon, Wael Jerro to lu ọmọ Naijiria ni gbanjo loju opo Facebook rẹ ti wa ni gbaga ọlọpaa.

Alaga ajọ to n ri si awọn ọmọ Naijiria ti wọn wa nilẹ okeere, Abike Dabiri-Erewa lo fidi ọrọ yii mulẹ loju opo Twitter rẹ.

Abike ṣalaye pe, ọkunrin naa yoo jẹjọ lẹyin tawọn ọlọpaa ti fi panpẹ ofin mu un.

O ni ijọba ilẹ naa yoo gbe e lọ si ileẹjọ nitori ijọba tako fifi ọmọ eeyan ṣe kata-kara.

Ọgbẹni Jerro polowo Busari Peace pẹlu iwe irina rẹ loju opo Facebook rẹ.

Ẹgbẹrun kan owo dọla($1,000) lo gbe le e lori.

Ọmọ ọgbọn ọdun ni ọmọ Naijiria naa, ipinlẹ Oyo ni o ti wa.

Ọpọ ọmọ Naijiria lo faraya lori ayelujara ti wọn si sọ pe ki ijọba ilẹ Lebanon fi ọwọ ofin mu un.