Pete Edoche: Elebuibon ní tá bá ṣọ́ra, àṣà àjèjì yóò sọ wá dẹrú òyìnbó

Oríṣun àwòrán, @theknot
Araba awo ilu Oshogbo, Oloye Ifayemi Elebuibon ti sọ pe, ki ọkunrin maa kunlẹ lati beere lọwọ ọrẹbinrin rẹ pe ko fẹ oun, kii ṣe aṣa ilẹ Yoruba,o ni iwa ajeji naa ni asa ọhun.
Elebuibon lo sọ ọrọ yii ninu ifọrọwerọ rẹ pẹlu BBC Yoruba, lori ọrọ ti ọkan lara awọn agba ọjẹ oṣere tiata lorilẹ-ede yii, Pete Edoche sọ pe, oponu ati ọdẹ ni ọkunrin to ba n kunlẹ fun obinrin lati beere pe, ko gba ki oun lee fi ṣaya.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Èlé owó iná ọba kọ́ ló kàn, ẹ kọ́ ṣàtúnṣe sí ìlànà àdánú tẹ́ ń ṣe fún wa - Iléeṣẹ́ apínná sọ fún ìjọba
- Àdínkù bá owó ojúmọ́ ọlọ́kadà l‘Ọyọ láti ₦200 si ₦100, owó gbígbà bẹ̀rẹ̀ lónìí
- A fẹ́ ìtọ́jú fún Boko Haram tó bá ronúpìwàdà, ẹ dá iléeṣẹ́ sílẹ̀ fún ìtọ́jú wọn - Ilé aṣòfin
- Olùkọ́ tó fi tipá gba ìbálé akẹ́kọ̀ọ́ tó fẹ́ wọ fásitì rí ẹ̀wọ̀n ọdún 21 he
- Fayose, o kò ní àmúyẹ gidi láti di ọmọ ẹgbẹ́ wa, àyè kò sí fún ọ - APC Ekiti
Oloye Elebuibon ni awọn oyinbo alawọ funfun lo ma n ṣe iru nnkan bẹẹ, ati pe ko si ninu aṣa ilẹ Yoruba.
O ni awọn oyinbo lo ma n ṣe bẹẹ, kii ṣẹ aṣa tiwa pẹlu afikun pe, ti ọkunrin ba fẹ gbeyawo laye ijọun nilẹ Yoruba, n ṣe lo maa n kọkọ ṣe iwaadi iru ile ti obinrin bẹẹ ti jade wa.

Oríṣun àwòrán, others
"Lẹyin naa alarena yoo tọ ẹbi obinrin ọhun lọ, kii ṣe pe ki ọkunrin mu oruka lọwọ, ko si kunlẹ lati beere pe ki obinrin fẹ ọhun."
Elebuibon tẹsiwaju pe, awọn obi obinrin lo yẹ ki ọkunrin dọbalẹ fun lati beere pe ,oun fẹ fi ọmọ wọn ṣaya, kii ṣe obinrin naa.
Ni ti aye to daye ọlaju, Elebuibon ni "Kii ṣe gbogbo nnkan ni a gbọdọ maa tẹle pẹlu ọlaju, a ko le sọ pe aye ti daye ọlaju, ka foju ẹgbo tẹ ilẹ."
Elebuibọn pari ọrọ pe, iwa ọlaju maa n koba eeyan ni, ti ko si n jẹ ki eeyan ni ami idanimọ gẹgẹ bi ọmọ ilẹ Yoruba atata.













