2020 budget: Inú mi dùn láti buwọ́lu owó ìṣúná Nàìjíríà l'ọ́jọ́ ìbí mi - Buhari

Oríṣun àwòrán, Facebook/professoryemiosinbajo
Aarẹ orileede Naijiria, Muhammadu Buhari ti buwọlu owo isuna ọdun 2020.
Bashir Ahmad to jẹ oluranlọwọ aarẹ lori ọrọ iroyin ayelujara fi fidio bi aarẹ ti ṣe buwọlu owo isuna naa soju opo Twitter rẹ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
Ṣaaju ni Aarẹ Buhari ti kede pe ojuṣe to dun mọ oun ninu ni lati bu ọwọ lu owo iṣuna ọdun 2020 ni ayajọ ọjọ ibi ọdun kẹtadinlọgọrin oun.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
Pẹlu igbesẹ yii, orilẹede Naijiria ti pada si lilo eto imurasilẹ ati amulo owo isuna laarin oṣu kini ọdun titi di oṣu kejila ọdun.
Oṣu Kẹwa ọdun 2019 ni aarẹ Buhari fi aba isuna owo naa ranṣẹ si ile aṣofin Naijiria.
Triliọnu mẹwa Naira ni iye owo isuna naa, ti awọn ile aṣofin Naijiria ti ṣaaju fi ọwọ si lẹyin ayẹwo.










