You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Sanwo Olu: Gomina Ìpínlẹ̀ Eko kọ ‘Your Excellency’ fún ‘Mr Governor’
Ọpọlọpọ awọn gomina ti wọn ti jẹ ni ẹkun Iwọ- oorun orilẹ-ede Naijiria lo ti fi igba kan sọ wi pe awọn ko fẹ ki wọn ma a pe wọn pẹlu oye ọlọla julọ 'Your Excellency' ṣaaju orukọ wọn.
Ọpọlọpọ awọn gomina yii maa n lo awọn orukọ naa lati sunmọ ara ilu ati ki ibaṣepọ to danmọran le wa laarin awọn ati awọn ara ilu.
Laarọ oni ni awọn ọmọ Naijiria bẹrọ si ni fun Gomina Ipinlẹ Eko lesi, lẹyin ti oun naa pinnu pe oun ko fẹ 'Your Excellency' mọ lara orukọ oun pe 'Mr Governor' ni oun fẹ ma a jẹ.
- Ọ̀gẹ̀dẹ̀ ń bàjẹ́..; Akẹ́kọ̀ọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ 12 gbà èèyàn láti kọ ìdánwò fún wọ́n
- Òògùn tọ́jọ́ fẹ́ lọ lórí wọn ni àjọ SACA ń rà lábẹ́ àkóso aya Ajimobi - Seyi Makinde
- Ó ṣe jẹ́ ṣọ́ọ́bù aláṣọ kanṣoṣo ni iná tí maa ń ṣẹ́yọ lọdọọ́dún lọ́jà Balogun?
- Bí alárùn Ebola bá wọ Nàíjíríà, kò sí gìrì, a ti múra sílẹ̀ láti paná rẹ̀ - Àjọ NCDC
Idi ti gomina naa fi lede ni wi pe 'Your Excellency' ti bu iyi kun ipo oun ju iṣẹ to wa nibẹ lọ.
Ati wi pe oun wa lati wa ṣiṣẹ ni ipinlẹ Eko ni, nitori naa ti awọn eniyan ba n pe oun ni 'Mr Governor' yoo ma a ran oun leti idi ti oun fi wa ni ipo ti oun wa lọwọlọwọ.
Lara awọn gomina to ti ko 'Your Excellency' ni iwọ-oorun ile Naijiria ni yii:
- Gomina tẹlẹri ni ipinlẹ Osun, Rauf Agbesola sọ pe orukọ ti oun fẹ ki awọn eniyan ma a pe oun ni 'Ogbeni' dipo 'Your excellency' nigba to wa lori oye.
- Bakan naa, Gomina Ipinlẹ Ondo, Arakunrin Oluwarotimi Akeredolu naa ṣọ nigba to de ipo gomina pe oun fẹ ki wọn pe oun ni 'Arakunrin' dipo 'Governor' niwaju orukọ rẹ
- Gomina Ipinlẹ Ekiti tẹlẹri, Ayodele Fayose ni awọn eniyan maa n pe ni 'Osokomọlẹ' dipo gomina
- Bola Ahmed Tinubu to jẹ Adari fun ẹgbẹ Oselu APC lorilẹ-ede Naijiria naa jẹ ọkan lara awọn eniyan ti orukọ ti awọn eniyan maa n pe e ni lọpọ igba ko nii ṣe pẹlu ipo to di mu, 'Asiwaju' ni awọn eniyan ma n pe e.
- Gomina tẹlẹri ni ipinlẹ Ogun, Gbenga Daniel ni awọn eniyan ma n pe ni 'Ogidi ọmọ' lọpọ igba dipo gomina.
Èrò àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ lórí Sanwo Olu tó ní kí wọ́n máa pe òun ní "Ọ̀gbẹ́ni Gómìnà"
Lẹyin ti gomina ipinlẹ Eko, Babajide Sanwo-Olu sọrọ loju opo Twitter rẹ pe ki awọn eeyan dẹkun lati maa pe oun ni ọlọlajulọ, ọpọ awọn Naijiria ti n fi erongba wọn lede lori ipinnu yii.
Sanwo-Olu ni oun fẹran ki wọn ma pe oun ni "Ọgbẹni Gomina," dipo Ọlọlajulọ.
Bi awọn kan ṣe ni ipinnu yii dara ni awọn mii n dẹyẹ si gomina ọhun, bẹẹ ni awọn mii n sọ fun un pe ọrọ akọle kọ lokan bayi, bi ko se ki gomina naa ṣe ohun ti awọn ara ilu n fẹ.
Awọn bii Paul Ogwa lori Twitter fara mọ ipinnu yii, wọn gboriyin fun Sanwo Olu pe:
Aisha Remi-Adedeji sọ pe ko sohun to kan ẹnikẹni nitori orukọ to wu koowa lo le jẹ́:
- Olujinmi ló borí ìbò fẹ́kùn gúúṣù Ekiti, Adeyeye gba ile lọ - Iléejọ́ Kòtẹ́milọ́rùn ṣèdájọ́
- Osinbajo kìí ṣe amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ Buhari tí yóò máa gbé ìwé lọ fun ní London - Akin Alabi
- Ẹ̀yin òbí, ẹ má kó àwọn ọmọ yín lọ síbùdó atúnwàṣe mọ́ - Seyi Makinde
- Yóò jé ohun tó burú tí Nàìjíríà bá da ikọ́ agbábọ́ọ̀lù Golden Eaglets nu - Onigbinde
Ni ṣe ni Babajide Adebajo ni tirẹ fi Gomina ọhun ṣe yẹyẹ pe aṣeyọri nla ni orukọ tuntun.
Omonefe Wisdom Omare ni tirẹ sọ pe, yiyi akọle gomina pada ko da nkan nitori ki si anfani ti yoo ṣe fun awọn ara ilu.
Salawu Enitan loju opo Facebook ni, Gomina ipinlẹ Ọṣun ana, Rauf Aregbesola ti ṣe iru ohun bayin ri, nitori naa, ko jẹ tuntun.
Ẹ wo awọn ohun miran tawọn eeyan tun sọ loju opo Facebook nipa ipinu Gomina yii.