Kogi Loan: Owó àkànṣe ìṣẹ́ ìjọba àpapọ̀ tíjọ́ba Kogi ṣe la fẹ́ dá padà

Gomina Yahaya Bello ati MUhammadu Buhari

Oríṣun àwòrán, @A_Oshiomhole

Aarẹ Buhari ti kọ lẹta si ile aṣofin agba lati beere owo to le ni biliọnu mẹwa naira fun ipinlẹ Kogi.

Ninu lẹta kan to kọ si aarẹ ile aṣofin agba Ahmad Lawan, Aarẹ Buhari ni oun fẹ san owo naa fun ijọba ipinlẹ Kogi, ko lee san owo oṣu to jẹ labẹle.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Buhari ṣalaye fun awọn aṣofin agba pe gbese owo awọn akanṣe iṣẹ to jẹ ti ijọba apapọ, eleyii ti ijọba ipinlẹ Kogi na owo le lori ni oun fẹ fi owo naa san.

Gomina Yahaya Bello ati MUhammadu Buhari

Oríṣun àwòrán, @A_Oshiomhole

Amọṣa, aarẹ ile aṣofin agba ti fa lẹta naa le igbimọ tẹẹkoto lori ọrọ gbese abẹle ati toke okun fun amojuto to ba yẹ ki o si jiṣẹ pada fun ile naa ni ọsẹ meji.

Ipinlẹ Kogi yoo wọ inu agbami eto idibo gomina ni oṣu kọkanla pẹlu oniruuru iroyin nipa gbese ti wọn ni ijọba jẹ oṣiṣẹ nibẹ.