Bobrisky: Ogunye ní ìwà ìṣekúpani láìtọ́ wúwo ju ọ̀rọ̀ ‘kòsakọ́-kòṣabo’ lọ

Oríṣun àwòrán, Instagram/bobrisky222
Ko sọrọ kankan ninu ohun tawọn kan sọ pe o yẹ ki awọn ko ṣakọ ko ṣabo ni ile igbọnsẹ tiwọn lawujọ, paapaa ni papakọ ofurufu ati awọn ibo miiran lawujọ.
Ilumọọka agbẹjọro, Jiti Ogunye to ba BBC sọrọ lo fidi ọrọ yii mu lẹ. Ogunye ni "melo ni eeyan bi Bobrisky lorilẹede Naijiria ti ijọba yoo fi kọ ile igbọnsẹ ọtọ fun wọn."
Agbẹjọro Ogunye ni, ọrọ runrun lọrọ naa nitori iṣoro to n koju orilẹede Naijiria pọ ju pe, ki ẹnikan maa sọ pe o yẹ kawọn ko ṣakọ, ko ṣabo ni ile igbọnsẹ ti wọn lọtọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ilé aṣọ̀fin Nàìjíríà ń gbèrò ẹ̀wọ̀n f'áwọn olùkọ̀ tó bá dẹnu ìfẹ́ kọ akẹ́kọ̀bìnrin
- Wo ìdí to fi gbọdọ̀ yàgò fún Bobrisky, akọ tó ń ṣe bíi abo
- Ọmọ Nàìjíríà ti le è sọ̀rọ̀ jù, owó orí gbọdọ̀ gun ìpè lórí fóónù - ìjọba àpapọ̀
- Tọkọtaya ọmọ Nàíjíríà rugi oyin torí wọ́n ń ta ìpara ìbóra lórí ayélujára
- "Èmi ò r'óhun tó burú kí obìnrin opó fẹ́ ọkọ míì sínú ilé ọkọ rẹ̀"
Amofin Ogunye ṣalaye pe, ofin ilẹ Naijiria gan an ko faye gba awọn ko ṣakọ ko ṣabo, nitorinaa, iru eleyi ko le fẹsẹ mu lẹ.
Ijọba apapọ lo kọkọ fi ikilọ lede nipa ewu to wa ninu kawọn eeyan bii Bobrisky maa ba awọn obinrin lo ibudo igbọnsẹ papọ.

Oríṣun àwòrán, Facebook/Miss Sahahra
Ikede yii waye lẹyin ti rogbodiyan ṣẹlẹ ni papakọ ofurufu Nnamdi Azikwe ni ilu Abuja, nigba ti wọn ri Bobrisky to n lo yara igbọnse awọn obinrin.
Ijọba wa rọ ẹka ilera lorilẹede Naijiria lati la awọn eniyan lọyẹ nipa ewu to wa ninu lilo yara igbọnse kan naa pẹlu Bobrisky, ti awọn eeyan kan si daba pe, ki wọn pese ile igbọnsẹ ọtọ fun awọn eeyan to jẹ ‘Kosakọ-Kosabo’ bii Bobrisky ati Miss Sahhara lawọn ibudo ajọlo.
- Àtúpalẹ̀ àbá ètó ìsúná ọdún 2020 rèé, wo bó ṣe kàn ọ́ sí
- Mo gbàgbọ́ pé ọmọ mi kò kú, mo ṣì ń wá a - Bàbá Akẹ́ẹ̀kọ́ fásitì Akungba
- Fásitì Ghana lé olùkọ́ méjì tí àṣírí wọ́n tú lórí ẹ̀sùn ìbálòpọ̀ lọlé
- Òótọ́ ni Iyabo Ojo ń sọ́! Ìdójútì gbàá ni kí Òṣèré máa tọrọ owó tórí àìsàn - Femi Adebayo
- Ìjọba, ẹ yé fi ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn dun ọmọ Nàìjíríà mọ́- SERAP
Ṣugbọn amofin Ogunye ni awọn iṣẹlẹ bi awọn ọlọpaa ti wọn n ko awọn ara ilu satimọle lainidi, ọna ti ko dara, iṣekupa awọn ọmọ Naijiria lorilẹede India lo yẹ ki ijọba wa nnkan ṣe si bayii.

Oríṣun àwòrán, Instagram Bobrisky222
Agbẹjọro Ogunye ṣalaye siwaju si pe, ofin Naijiria si n ri Bobrisky gẹgẹ bi ọkunrin ayafi to ba lọ ṣe ibura nile ẹjọ pe oun fẹ yipada lati ọkunrin si obinrin.
O fikun ọrọ rẹ pe awọn agbofinro lẹtọ lati fọwọ ofin mu un to ba lọ si ile igbọnsẹ awọn obinrin ni Naijiria.












