FIRS: Ijọba Nàìjíría ṣetan láti bẹ̀rẹ̀ si ni gbowó orí lóri ìbáraẹnisọ̀rọ̀

Álága ilé iṣẹ́ tón gbowo orí lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà (FIRS), Babatunde Fowler tií ni báyìí o, ko si ǹkan to buru ninu kí ìjọba máá gba owo orí fún ìbáraẹnisọ̀rọ̀ lori ẹ̀rọ.
Fowler sọ èyí di mímọ lásìkò tó n ba awọn akọroyin sọ̀rọ̀ níbi ìpàdé àpérò ètò ọ̀rọ̀ ajé Nàìjíríà tó wáye nilu Abuja.
"Ẹ jẹ́ kí n sọ báyìí, Ọmọ Nàìjíríà máa ń sọ̀rọ̀ púpọ̀ jùlọ, wọn a maa sọ̀rọ̀ ju bo ṣe yẹ ki wọ́n sọ̀rọ̀ lọ, ẹni to ba si lágbàra láti sọ̀rọ̀ to bi wọ́n ṣe ń sọ yìí tí a bá gbé owo ori lee, ko sí ǹkan to buru níbẹ̀"
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ilé aṣọ̀fin Nàìjíríà ń gbèrò ẹ̀wọ̀n f'áwọn olùkọ̀ tó bá dẹnu ìfẹ́ kọ akẹ́kọ̀bìnrin
- Ẹkún omí yalé, ó ṣekú pa ọmọ fásitì Akungba
- Òótọ́ ni Iyabo Ojo ń sọ́! Ìdójútì gbàá ni kí Òṣèré máa tọrọ owó tórí àìsàn - Femi Adebayo
- Mi ò gbọ́ pé Akeredolu ti yọ mí nípò gẹ́gẹ́ bíi Olùbádámọraǹ rẹ̀ - Pelemo
- Olùkọ́ míì ní fásitì Eko, Samuel Ọladipọ tún ń bèèrè ìbálòpọ̀ lọ́wọ́ akẹ́kọ̀ọ́
"A máa fi ara wa we àwọn orilẹ̀-ède to ti tó tán, sùgbọ́n ìdá méji ninu ìdá ọgọ́rùn ni Ghana ń gba lówó orí fún ìbáraẹnisọ̀rọ̀, wọ́n si maa n lo ǹkan ti wọn ba ri níbẹ̀ láti gba bùkáta àwọn fásìtì wọ́n, èyí si lo mu ki àwọn ọmọ Nàìjíríà lọ maa kawe ni Ghana."

Ní báyìí àwọn asòfin n pète ìdá mẹsàn fún owó ori ibaraẹni sọ̀rọ̀ láti fi rọ́pò ida meji owo ti ìjọba gbe lé ọjà rírà láìpẹ́ yìí.
- Fídíò rèé nípa bí Aláké tuntun ṣe ń gba ìwúre lábẹ́ Olúmọ kó tó gba adé
- Rashidi Ladọja ṣe ọjọ́ ìbí alárinrin, Ibadan mì tìtì
- Mo sọkún nípa fídíò BBC torí ó jẹ́ ìtàn tó ti ṣẹlẹ̀ sí mi rí - Bisi Fayemi
- Ìdájọ́ àkọ́kọ́ kò tẹ́ mi lọ́rùn, mo tún tí gbé Seyi Makinde lọ silé ẹjọ́ - Bayo Adelabu
- Njẹ ààbo wà fún Buhari nílé aṣòfin àpapọ̀ bi yoo se gbé àbá isúna kalẹ lónìí ?
Fowler tún sàlàye lóri owó ori ti wan fi le ọjà rírà lori ayélujara pé gbogbo àwọn ti wan ń lo ayelujara láti ta ọjà wọ́n ni àwọn banki yóò ti maa yọ ìdámarun ninu ǹkan ti wọ́n ba ta, láti fi sọ̀wọ si FIRS.








