Oyo Election Tribunal: Adelabu tún gbé Seyi Makinde lọ sí ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn

Adelabu ati Seyi Makinde

Oríṣun àwòrán, OTHERS

Àkọlé àwòrán, Bayo Adelabu ti ẹgbẹ́ òsèlú APC ní òun kò faramọ́ ìdájọ́ Àjọ Elétò Ìdìbò tó ní Seyi Makinde ló wọlé nínú ìdibò tó kojá.

Oloye Adebayo Adelabu ti ẹgbẹ oselu APC ti ni, oun ko faramọ idajọ ajọ eleto idibo to da igbẹjọ oun nu lori idibo to gbe Seyi Makinde wọle gẹgẹ bi gomina nipinlẹ Ọyọ.

Lẹyin ọjọ mọkanlelogun ti idajọ naa waye ni ilu Ibadan, ni Adelabu gbe ẹjọ lọ ile ẹjọ kotẹmilọrun.

Adelabu ati ẹgbẹ oselu APC sọ wi pe, magomago waye ninu idibo Ọjọ Kẹsan, Osu Kẹta, ọdun 2019, eleyii to gbe Seyi Makinde wọle gẹgẹ bi gomina.

Adelabu wa n beere lọwọ ile ẹjọ kotẹmilọrun lati sọ wi pe oun lo ni ibo to pọju lọ ninu idibo sipo gomina ni ipinlẹ Ọyọ abi ki wọn tun ibo naa di.

Ti a ko ba gbagbe, Alaga igbẹjọ naa, Justice Muhammed Sirajo salaye pe awọn da ẹjọ ti APC pe mọ Seyi Makinde nu nitori gbogbo awọn ẹlẹri ti Adelabu pe ko ni ẹri to daju, amọ ti wọn n sọ ahesọ lasan.