Ọ̀gá ọlọ́pàá pàṣẹ kí wọ́n ṣé ìwádìí ọlọ́pàá inú àwòrán 4+4

Aworan awọn ọlọpaa

Oríṣun àwòrán, @kekeTony

Àkọlé àwòrán, Ṣadede ni aworan awọn ọlọpaa ti wọn na ika 4+4 yi lu sita loju opo ayelujara
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Adele ọga ọlọpaa lorileede Naijiria Mohammed Adamu ti pasẹ ki ẹka to n ṣewadi nnkan aworan bẹrẹ iwaadi lori aworan awọn ọlọpaa mta kan ti wọn jọ bi ẹ ni naka soke lati ṣe atilẹyin fun ẹgbẹ oṣelu APC ati Aarẹ Buhari to n du ipo lẹẹkansi.

Loju opo Twitter ileeṣẹ naa ni wọn fi ikede yi si lọjọ Aje.

Gẹgẹ bi ohun ti ikede naa sọ,bi wọn ba ti pari iwaadi na wọn yoo fi abajade rẹ sita fun gbogbo ara ilu.

Àkọlé fídíò, Àjọ Ọlọ́pàa Naijiria: A ó fi òsìsẹ́ SARS tó se isẹ́ ibi náà jófin

Ohun to ṣe okunfa iwaadi yi ko silẹyin bi arakunrin kan ti ṣe fiwe ranṣẹ si ileeṣẹ ọlọpa loju opo Twitter nipa aitọ iwa ti awọn ọlọpaa to na ika 4+4 naa hu.

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

Lẹnu ọjọ mẹta yi, awọn ọmọ Naijiria ti n bẹnu atẹ lu ileeṣẹ ọlọpaa fun bi wọn ti ṣe ni wọn n ṣegbe lẹyin ẹgbẹ oṣelu to wa ni ijọba.

Ọrọ naa lagbara pupọ lasiko igba ti ọga ọlọpaa ana ,Ibrahim Kpotun Idris , wa nipo ọga ọlọpaa.

Lasiko rẹ, ọpọ awuyewuye waye laarin awọn oloṣelu paapa awọn ti ile asofin agba to fi mọ awọn ajafẹtọmọniyan kan ti wọn jijọ wọya ija.

Igbesẹ adele ọga ọlọpaa tuntun yi yoo ma ṣe afihan boya nnkan ti yi pada tabi oun naa n ṣe bi ẹni gbe lẹyin ẹgbẹ oṣelu kan.