#NigeriaDecides2019: ‘Kò sí àríyá lónìí, kò tún sí ìbò dídì, irú Sátidé mímọ́ wo rèé’

An agunbaniroto fẹ sisẹ ibo to sun silẹ

Oríṣun àwòrán, Ronke Fajerokun

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Kii se iroyin mọ pe ajọ eleto idibo nilẹ wa, INEC, ti wọgile eto idibo aarẹ to yẹ ko waye lọjọ Satide oni.

Ni kete tawọn ọmọ Naijiria si ti gbọ iroyin agbọgbọntinu ọhun ni wọn ti n sọ oniruuru ero wọn nipa ikede yiii.

Lori awọn opo ikansiraẹni lori ayelujara bii Facebook, Twitter, Instagram ati Whats App, ẹnu ko gba iroyin nipa ohun tawọn eeyan n wi lori isẹlẹ yii.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Lara awọn ohun ti wọn kọ to pa ni lẹrin ni bi awọn eeyan kan se ni orilẹede Naijiria su awọn, ti wọn si n wa ọna lati tẹ ọkọ leti lọ soke okun.

Lawọn oju opo Facebook, igbe to gba ibẹ kan ni pe ‘Ko si ayẹyẹ igbeyawo ta fẹ lọ loni ọjọ, ko si ayẹyẹ oku sise, ko si ibi kankan ta fẹ lọ, wọn tun wa ni a ko lee dibo mọ. Iru Satide mimọ wo ni eyi lorilẹede Naijiria.’

Iha tawọn eeyan kọ si isunsiwaju ibo

Oríṣun àwòrán, Ronke fajemirokun

@raph_shalom, ọpọ ibeere lo n beere lati sa kuro ni Naijiria.

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

@d_boy_nextdoor, o ni orilẹede Naijiria nikan lati lee gbọ iru iroyin YajoYajo bayii, to si fi aworan kan to pa ni lẹrin sidi rẹ.

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2

Ademola Aremu lori Facebook ni ‘o seni laanu pe awọn wolii ariran wa ko ri saaju pe ajọ eleto idibo yoo sun ibo siwaju ni Naijiria sugbọn awọn ti yoo bori ibo ni wọn n ri.’

Iha tawọn eeyan kọ si isunsiwaju ibo

Oríṣun àwòrán, Ademola Aremu

Bakan naa ni awọn eeyan orilẹede Ghana tun n fi wa se yẹyẹ ni Naijiria lori ba se sun ibo aarẹ siwaju lọjọ idibo gangan.

IssahakuB.Gbene lori Facebook ni ‘Awọn ọmọ Naija yii saa, Wọn ko lee se raisi Jọllọfu, bẹẹ ni wọn ko tun lee seto idibo lasan. Yatọ si ẹba ati ọbẹ ewuro tẹ mọ se, ki lẹ tun lee se gan?

Iha tawọn eeyan kọ si isunsiwaju ibo

Oríṣun àwòrán, iSsaku B.Gbene