Shehu Sani: Màá kéde ẹgbẹ́ òṣèlú tí mo máa darapọ̀ pẹ̀lú láìpẹ́

Oríṣun àwòrán, Shehu Sani
Shehu sani ti kede pe oun ko tii darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu kankan lẹyin ti oun fi ẹgbẹ oṣelu APC silẹ ni ọjọ abamẹta.
Sẹnetọ Sani kede lori ikanni Twitter rẹ lọjọ aiku pe laarin ọjọ meji si asiko yii ni oun yoo sọ ni pato, ibi ti oun yoo ko ẹru oṣelu oun gba lọ.
Bakan naa lo fi da awọn ololufẹ rẹ loju pe oun yoo dije lasiko idibo apapọ to n bọ
Sẹ́nétọ̀ Shehu Sani ti fi ẹgbẹ́ òṣèlú APC sílẹ̀

Sẹnetọ to n ṣoju ẹkun idibo aarin gbungbun Kaduna nile aṣofin agba Naijiria, Shehu Sani ti fi ẹgbẹ All Progressives Congress, APC, silẹ.
Ninu lẹta kan to kọ si alaga apapọ ẹgbẹ APC, Sani sọ pe ẹgbẹ APC ko faaye gba awọn afojusun ati iran rere toun ni fun eto isṣejọba awaarawa Naijiria lati wa si imuṣẹ, nitori awọn iwa oṣelu abẹle.
Sani sọ pe oun fi ẹgbẹ APC silẹ nitori pe awọn to wa ninu ẹgbẹ naa kundun lati maa tapa si ofin ẹgbẹ, ti awọn gomina si n ṣe boṣe wu wọn, ti wọn si tun lagbara ju Aarẹ Muhammadu Buhari lọ.
"Botilẹ jẹ pe mi o ri tikẹẹti ẹgbẹ APC gba lati tun dije fun ipo Sẹnetọ lẹẹkan si, eyi ko di mi lọwọ lati dije fun ipo naa l'ọdun 2019 nitori pe ọpọlọpọ ẹgbẹ oṣelu lo ti n ṣẹju si mi.
O ni oun ti kọkọ gbiyanju lati fi ẹgbẹ silẹ lasiko ti awọn akẹgbẹ oun kan ṣe bẹ, sugbọn ileri ti awọn adari ẹgbẹ naa ṣe fun un pe wọn yoo yanju awọn nkan to yẹ lati yanju, lo jẹ ki oun duro. Sugbọn ẹtan ni gbogbo rẹ jasi.
Ọrọ Sẹnetọ Sani ati gomina ipinlẹ Kaduna, Mallam Nasir El-Rufai dabi eku ati oloogbo lati ọdun 2015 ti wọn ti dibo yan wọn.
Paapa lati igba ti gomina naa ti ṣe atilẹyin fun Mallam Baba Sani lati di oludije fun ipo sẹnetọ ti Sani n fẹ.

Oríṣun àwòrán, Ijọba ipinlẹ Kaduna/Twitter
Sani ni olu ile ẹgbẹ APC nilu Abuja fọwọ si ṣaaju eto idibo abẹle, sugbọn ti gomina El-Rufai ati awọn olori ẹgbẹ naa ni ipinlẹ Kaduna kọ ọ.
Sugbọn ko sọ ẹgbẹ ti yoo darapọ mọ. O sọ pe ti asiko ba to, oun yoo kede rẹ.













