Ékìtì: Obìnrin mẹ́jì, ọkùnrin mọ́kànlélọ́gbọ̀n ń du ipò kan

Oríṣun àwòrán, TWITTER/APC
Idibo abẹle ti ẹgbẹ́ oṣelu APC n lọ lọwọ ni Ado Ekiti ní ipinlẹ̀ Ekiti
Ọkunrin ọgbọn ati obinrin meta ti jade lati du ipò gomina Ekiti lábẹ́ aṣia ẹgbẹ́ oṣelu APC ti yoo waye ni ọjọ kẹrinla oṣu keje.
Papa iṣere Oluyemi Kayode ni idibo naa ti n waye.
Gomina Ipinle Ekiti, Ayodele Fayose, ni oun kò bá má ti gbà wọn laaye láti lo ibẹ̀ bi ko ba ṣe ẹ̀mí ìfaradà fún alatakò ninu oṣelu ti òun ni.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
A gbo pe, awọn olukopa ninu idibo naa ju ẹgbẹrun meji lọ ati pe Gomina Ipinlẹ Nasarawa, Umaru Tanko Al-Makura, lo n ṣe agbatẹru rẹ.
Bẹẹ gẹgẹ ni awọn ọlọpaa yí gbogbo agbegbe naa ká lati pese aabo ni papa iṣere naa.

Oríṣun àwòrán, Abdullahi Garba Birnin Kudu
Oriṣiriṣi iroyin ni o ti n jade lati ibi idibo naa bayii.
Bi idibo naa ṣe n lọ lọwọ ni òjò ṣe bẹrẹ si ni rọ ti awọn olukopa si n bẹru pe ojo naa ko ni jẹ́ ki wọn pari idibo ọhun.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2

Oríṣun àwòrán, Abdullahi Garba Birnin Kudu
Bi òjò naa ṣe da ni idibo tun tẹ̀ s'iwaju.
Bakan naa ni ifẹnuko ẹgbẹ oṣelu naa ni awọn wọọdu, ijọba ibilẹ ati ipinlẹ ti a mọ si congress n waye bi idibo naa ṣe n lọ.












