You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Senegal Fire: Àwọn ọmọ tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ bí 11 pàdánù ẹ̀mi wọn lẹ́yìn iná tó ṣẹ́yọ
Àwọn ọmọ tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ bí mọ́kànlá pàdánù ẹ̀mi wọn lẹ́yìn iná tó ṣẹ́yọ.
Ọdun to kọja ni iru iṣẹlẹ naa waye ri ti ẹmi awọn ọmọ jojolo mẹrin lọ lẹyin ti ina jo raurau ni ẹka igbẹbi ni ile iwosan ọhun.
Pẹlu ibanujẹ ọkan ni Aarẹ Ilẹ Senegal, Macky Sall fi ṣalaye pe awọn ọmọ ikoko ti wọn ṣẹṣẹ bi mọkanla ti padanu ẹmi wọn ni ileewosan to wa ni iwọ ọọrun Tiyaouane.
Loju opo ikansiraẹni Twitter ni aarẹ naa ti salaye pe ina bẹ silẹ ni ẹka ileewosan awọn alaboyun ni ileewosan Mame Abdou Aziz Sy Dabakh.
- Àwa mẹ́ta la gbé òkú Timothy Adegoke lọ sí Ede road- Ẹlẹ́rìí Oyetunde Kazeem
- Ọmọ ọdún 19 tí wọ́n sọ sí ẹ̀wọ̀n nitorí ọ̀kadà tó sọnù ti kú
- Gbajúmọ̀ Olórin Banky W ti rí tíkẹ̀ẹ̀tì ẹgbẹ́ òṣèlú PDP gbà láti díje dupò aṣòfin
- Ìjọba kéde òfin kónílé-ó-gbélé ní ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́sàn-án ní ìpínlẹ̀ Anambra
- Mà á dá fijilanté sílẹ̀, òmìnira á wà fún ìjọba ìbílẹ̀ láti ná owó wọn- Oluwole Oluyede
- Ohun ìbànújẹ́ ló ṣẹlẹ̀ ní Anambra, ẹ dákún mi ò fẹ́ kẹ́nikẹ́ni fi oró ya oró lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà- Buhari
Awọn oloṣelu lorilẹede naa ni waya ina to baj̣e lo fa ina to sọ naa.
Gomina agbegbe ti iṣẹlẹ naa ti waye, Demba Diop Sy ni awọn ọmọ mẹta ni awọn ri yọ kuro ninu ina naa.
Mr Say sọ fun awọn oniroyin pe ina naa ja ranyin kaakiri lojiji ni, ti awọn panapana si tiraka lati pa ina naa.
Ileeṣẹ iroyin ti ijọba ni orilẹede naa ni wọn ṣẹṣẹ si ile iwosan naa pada ni.
Ninu atẹjade ti aarẹ naa ti ba awọn eniyan kẹdun lo ti ni akoko to ṣoro ni eyi fun gbogbo eniyan paapaa awọn ti iṣẹlẹ naa ṣẹlẹ si.
Bakan naa ni minisita fun eto ilera, Abdoulaye Diouf Sarr to n ṣepade lọwọ ni ipade Ajọ Eleto Ilera Lagbaye, WHO ni inu oun bajẹ si iṣẹlẹ naa ti oun si n pada bọ nile lati wa ba awọn eniyan kẹdun.
Amọ awọn oloṣelu ni ẹgbẹ oṣelu miran ti bu ẹnu atẹ lu ijọba pẹlu iwoye pe bawo ni ina ṣe maa si ni ileewosan ijọba.
- Àwa mẹ́ta la gbé òkú Timothy Adegoke lọ sí Ede road- Ẹlẹ́rìí Oyetunde Kazeem
- Ọmọ ọdún 19 tí wọ́n sọ sí ẹ̀wọ̀n nitorí ọ̀kadà tó sọnù ti kú
- Gbajúmọ̀ Olórin Banky W ti rí tíkẹ̀ẹ̀tì ẹgbẹ́ òṣèlú PDP gbà láti díje dupò aṣòfin
- Ìjọba kéde òfin kónílé-ó-gbélé ní ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́sàn-án ní ìpínlẹ̀ Anambra
- Mà á dá fijilanté sílẹ̀, òmìnira á wà fún ìjọba ìbílẹ̀ láti ná owó wọn- Oluwole Oluyede
- Ohun ìbànújẹ́ ló ṣẹlẹ̀ ní Anambra, ẹ dákún mi ò fẹ́ kẹ́nikẹ́ni fi oró ya oró lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà- Buhari
- Àwọn ọmọ tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ bí mọ́kànlá pàdánù ẹ̀mi wọn lẹ́yìn iná tó ṣẹ́yọ
- Oriyomi Hamzat wọ gbaga ọlọ́pàá nítorí ọ̀rọ̀ Timothy Adegoke tó kú sílé ìtura Rahman Adedoyin
- Wo ojú àwọn tó fẹ́ díje dupò gómìnà lábẹ́ ẹgbẹ́ APC ní ìpínlẹ̀ Oyo lónìí
Ọdun to kọja ni iru iṣẹlẹ naa waye ri ti ẹmi awọn ọmọ jojolo mẹrin lọ lẹyin ti ina jo raurau ni ẹka igbẹbi ni ile iwosan ọhun.
Ti obinrin alaboyun kan si ku toyun-toyun lẹyin to jẹ irora fun ogun wakati, ki o to ṣ̣eṣẹ fẹ se iṣẹ abẹ amọ ati oun ati ọmọ inu rẹ lo gbẹmi mi.