You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Nnamdi Kanu trial: Adájọ́ sún ìgbẹ́jọ́ olórí ẹgbẹ́ IPOB Nnamdi Kanu sí oṣù tó ń bọ̀
Ileẹjọ giga ijọba apapọ niluu Abuja ti sun igbejọ Nnamdi Kanu siwaju si ọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu keji ọdun 2022 yii.
Ileẹjọ ni eyi yoo fawọn ni aye lati wo ibeere awọn agbẹjọro Kanu ti wọn ni ki ileẹjọ yi ọrọ olupẹjọ danu.
Adajọ tun sọ pe awọn olupẹjọ gbọdọ fi gbogbo ẹsun ti wọn fi kan Kanu to awọn agbẹjọro rẹ leti o kere tan bi ọrọ marun un si igbẹjọ.
- Ẹlẹ́ṣin tó gbé òkú Ọba Wukari pọ̀n wọ inú igbó rèé o! Ó sọ ìrírí rẹ ó sì tún já irọ ìròyìn orí ayélujára nípa rẹ̀
- Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ mánigbàgbé tó wáyé lọdún 2021
- Ṣé lóòtọ́ ni gómìnà ìpínlẹ̀ Abia àti Imo wọ àṣo àsíí Biafra bí o ṣe jáde lórí ayélujára?
- Ọlọ́run Tinubu kìí ṣé Ọlọ́run témi torínáà mi o ní gbè lẹyìn rẹ̀ ní 2023- Ojudu
- Ilé ẹjọ́ gbà béèlì ìgba mílíọ̀nù Naira(N200m) lórí ẹsùn tí EFCC fi kàn Mompha
- Wo Mẹkáníìkì alápá kan tí ayé ń pariwo pé o mọ ìjánu ọkọ̀ ṣe púpọ̀
Eleyii ṣẹlẹ lẹyin ti Kanu sọ pe oun ko jẹbi awọn ẹsun ti ijọba tun ṣẹṣẹ fi kan oun.
Amọ awọn olupẹjọ ni awọn ṣetan lati tẹsiwaju pẹlu ẹjọ naa wi pe awọn ni ẹlẹri meji.
Amọ, Mike Ozekhome to jẹ agbẹjọro Nnamdi bẹ ileẹjọ lati yi ẹbẹ awọn olupẹju danu.
Agbẹjọro Ozekhome tun sọ fun ileẹjọ lati gba beeli Nnamdi.
Adajọ sọ pe ki awọn olupẹjọ gbe ọrọ agbẹjọro Kanu to ni ki ileẹjọ yyi ọrọ wọn danu wo.
DSS, ẹ jẹ́ kí Kanu pààrọ̀ aṣọ tó ń wọ̀ wá sílé ẹjọ́ mi bí bẹ́ẹ̀ kọ́.......- Adajọ Binta Nyako
Wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nílé ẹjọ́ lónìí lórí ọ̀rọ̀ Kanu lẹ́yìn tó sọ pé òun kò jẹ̀bi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn án.
Nnamdi Kanu ko sọ pe oun jẹbi abi oun ko jẹbi awọn ẹsun tuntun ti ijọba apapọ fi kan an bi wọn ṣe sun igbẹjọ to bẹrẹ lóòní sí ọla, ọjọ kọkandinlogun oṣu kini ọdun 2022.
Awọn agbẹjoro Kanu sọ fun Onidajọ Binta Nyako pe awọn ni lati wo ẹsun tuntun naa finifini ki wọn si tun ni gbolohun pẹlu onibara wọn fun esi to yẹ.
- Wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nílé ẹjọ́ lónìí lórí ọ̀rọ̀ Kanu lẹ́yìn tó sọ pé òun kò jẹ̀bi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn án
- Alao Akala: Àhesọ lásán ni déètì ìsìnkú Feb 18 tẹ́ẹ gbọ́ o, ohun tí mọ̀lẹ́bí sọ gangan rè
- Ọlọ́run Tinubu kìí ṣé Ọlọ́run témi torínáà mi o ní gbè lẹyìn rẹ̀ ní 2023- Ojudu
- 'Ìwọ tóo bá ní Sabuké ìwé mẹ́wàá, kò yẹ kóò súnmọ́ dídu ipò òṣèlú kankan'
- Ǹjẹ́ obìnrin leè di "virgin" padà bí kò bá ní ìbálòpọ̀ fún ìgbá pípẹ́? - Onímọ̀ nípa ìbálòpọ̀ bá BBC sọ̀rọ̀
Eleyi lo mu ki ile ẹjọ wa sun igbẹjọ sí ọla, ọjọ kọkandinlogun oṣu kini ọdun 2022 ki awọn agbẹjọro Kanu le fi oju ṣunnukun wo ẹsun tuntun naa.
Ogbontarigi agbẹjọro, Mike Ozekhome ni o dari ọpọlọpọ awọn agbẹjọro fun Kanu bi igbẹjọ naa ṣe bẹrẹ loni ọjọ kejidinlogun oṣu kini ọdun 2022.
- Ẹ yìnbọn pa ẹnikẹ́ni tó bá ṣe ìkọlù sí ọ̀gbà ẹ̀wọ̀n- Mínístà Aregbesola
- Wo ohun tó ṣẹlẹ̀ nílé ẹjọ́ lónìí lórí ọ̀rọ̀ Kanu lẹ́yìn tó sọ pé òun kò jẹ̀bi ẹ̀sùn tí wọ́n fi kàn án
- Fayose, Olujimi, Oni ń forígbárí nítorí ìdìbò wọ́ọ̀dù tó wáyé lẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP l'Ekiti
- Lóòtọ́ ni àrùn Lassa ti wọ ìpìnlẹ́ Oyo, àmọ́ ẹ má mikàn - Ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo
- Àwọn gómìnà PDP parí ìpàdé, wọ́n ní Buhari ti dojú ọrọ̀ ajé Nàìjíríà rú
Wo ibi tí ọ̀rọ̀ Nnamdi Kanu dé dúró nílé ẹjọ́ lónìí
Igbẹjọ Kanu ni o n tẹsiwaju ni ọjọ Isẹgun, ọjọ kejidinlogun oṣu kini ọdun 2022 ni ile ẹjọ giga ilu Abuja.
Kanu ni o n koju ẹsun ikogunja ijọba, igbesunmọmi, igbiyanju lati ya ẹya kan kuro lara ilẹ Naijiria pẹlu pe o jẹ ọmọ ẹgbẹ IPOB ti ijọba ti fi ofin de.
- Fayose, Olujimi, Oni ń forígbárí nítorí ìdìbò wọ́ọ̀dù tó wáyé lẹ́gbẹ́ òṣèlú PDP l'Ekiti
- Ibà Lassa tún ti ń sọṣẹ́ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà
- Àwọn gómìnà PDP parí ìpàdé, wọ́n ní Buhari ti dojú ọrọ̀ ajé Nàìjíríà rú
- Wo àwọn ọmọ Yorùbá mẹ́fà tí ẹnu ń kùn lórí ìbò ààrẹ ọdún 2023
- Ọkùnrin kan gún ìyàwó rẹ̀ ọlọ́mọ mẹ́jọ pa nítorí pé ó ń ti ilẹ̀kùn mọ́rí
Wọn tun fi ẹsun kan pe o gbe iroyin ẹlẹjẹ nipa aarẹ Muhammadu Buhari eyi ti Kanu nipe oun ko jẹbi awọn ẹsun yii.
Awọn agbẹjọro Kanu fi idi re mulẹ pe lootọ ni ijọba apapọ fi awọn ẹsun tuntun kan ni bi wakati mẹrinlelogun ki igbẹjọ rẹ to bẹrẹ.
Igbẹjọ Kanu ma waye ni ọjọ kejidinlogun, ketadinlogun ati kerindinlogun oṣu kini ọdun 2022.
Ile ẹjọ Onidajọ Binta Nyako ni Igbẹjọ Kanu ti n waye ni ilu Abuja.
Igbẹjọ yii ni o waye lẹyin ọpọlọpọ ọjọ ti Ààre Buhari sọ wipe oṣelu kọ ni oun yoo fi yanju ọrọ Kanu afi ki o lọ wẹ orukọ ara rẹ mọ ni ile ẹjọ.