You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Olubadan , Oba Saliu Adetunji rọ Báàlẹ̀ Lagelu Abọke, Oloye Saheed Alatise kúrò lóyè lórí ẹ̀sùn aṣemáṣe
Olubadan ti ilẹ Ibadan, Ọba Oba Saliu Adetunji ti yọ Oloye Saheed Alatiṣe nipo gẹgẹ bi i Baalẹ Lagelu Abọke ni ijọba ibilẹ Ido ipinlẹ Ọyọ.
Atẹjade ti awọn oniroyin ri gbamu lati ọwọ ẹni ti o jẹ agbẹnusọ fun Ọba Alade naa, Adẹọla Ọlọkọ ṣe alaye pe iyọninipo Baalẹ naa ti bẹrẹ lẹsẹkẹsẹ.
Lara awọn iredi ti igbesẹ naa fi waye ni ẹsun ti wọn fi kan Baalẹ naa ni pe o kopa ninu rogbodiyan kan to waye ninu oṣu kẹẹsan ọdun 2017, lẹyin ti wọn fi jẹ Baalẹ tan.
- Nkechi Blessing sọ̀rọ̀ nípa ikú ìyá rẹ̀, ó tún tú àṣírí kàbìtì nípa ìhùwàsí ara rẹ̀ táyé kò mọ̀
- Kìí ṣe pé ìjọba ń fi ọwọ́ jẹ́jẹ́ mú àwọn jàndùkú o - Lai Mohammed
- Ṣé lóòótọ́ ní pé EFCC mú ìyàwó Gómìnà Ganduje ìpínlẹ̀ Kano
- Òjò alágbára rọ̀ ní Ikare-Akoko, ilé àádọ́jọ bá a lọ, èèyàn kan tún kú
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Ogun wó iléẹ̀kọ́ Nazareth High School, Imeko tó wó pa ọmọ orùkan
- Àwọn dókítà tí fagilé ìyanṣẹ́lódì ọlọ́jọ́ gbọọrọ, sùgbọ́n...
- Ṣé Facebook, Instagram, WhatsApp ti yín náà ti dẹnukọlẹ̀? Ìdí tó fi ṣẹ́lẹ̀ rèé...
- Ẹ yé kóra jọ pọ̀ láti d'ẹ́rù ba ni pé ọwọ́ Yorùbá ni Ààrẹ 2023 gbọ́dọ̀ bọ́ sí- Shekarau
- À ò ni gbárùkù tì gbogbo ẹ̀yin gómìnà ìhà Gúúsù tó bá tako kíkẹ́ràn jẹ̀ - Miyetti Allah
Igbimọ lọbalọba Olubadan fi kun ọrọ wọn wi pe bi Baalẹ naa ṣe kọ lati wa wi tẹnu rẹ lori awọn ọkanojọkan ẹsun ti wọn fi kan an lo jẹ iwa arifin gbaa si Olubadan ti ilẹ Ibadan
Wọn ni iru iwa arifin yii yẹ fun ijiya ninu ilana aṣa ati iṣe ilẹ Ibadan.
Lara awọn ẹsun mii ti wọn fi kan Baalẹ ti wọn rọ loye naa ni pe o gba ọna eru lati fa ara rẹ kalẹ fun oye Baalẹ nigba ti ki i ṣe ojulowo ọmọkunrin ti wọn bi sinu idile naa.
- Wo ewu tó wà nínú fífi ọṣẹ ìfọyín àti omi gbígbóná ṣe ìtọ́jú okùn tó so olúbi pọ̀ mọ́ ìyá ọmọ
- Kàyééfì! Ẹ wó ìyàwó tó ṣán ọkọ rẹ̀ mọ́lẹ̀ tó sí fí àdá bẹ orí rẹ̀!
- Ṣé o ti gbọ́ nípa ìlú tí ara sísan ti jẹ́ dandan fún àwọn ọmọbìnrin?
- Àwọn agbègbè ní ìpínlẹ̀ Eko rè é tí kò ní gbádùn iná ọ̀ba fún ọ̀sẹ̀ mẹ́jọ...
- Àyájọ́ Olùkọ́ lágbayé-Nígbà wò ní owó oṣù tuntun fáwọn olùkọ́ yóò di gbígbà?
- Ṣé lóòótọ́ ní pé EFCC mú ìyàwó Gómìnà Ganduje ìpínlẹ̀ Kano
- Ẹ gbà wá! Boko Haram ti gba ọ̀pọ̀lọ̀pọ̀ ìlú tán ní ìpínlẹ̀ Niger tí kò jínà sí Abuja
Ninu iwe kan ti awọn ẹbi Lagelu Abọke kọ si Olubadan ẹleyii ti olori ẹbi naa, Ganiyu Oladokun Okerinu Aboke buwọ lu ni wọn ti tọka rẹ pe Arakunrin Saheed Alatiṣe ti o wa lati Agbede Adodo nilu Ibadan ko lẹtọ lati ṣoju mọlẹbi Abọke ni to n bẹ ni agbegbe Bẹẹrẹ, gẹgẹ bi i Baalẹ.