Buruji Kashamu: Gómínà Dapo Abiodun tí lọ ṣàbẹ̀wò ìbánikẹ́dùn sí àwọn ẹbí Kashamu

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 6

Gomina ipinlẹ Ogun, Dapo Abiodun ti sapejuwe Sẹnetọ Buruji Kashamu gẹgẹ bi ẹni to ni ifẹ ọmọniyan.

Kashamu lo ṣoju ila orun ipinlẹ Ogun laarin ọdun 2015 si ọdun 2019.

Abiodun sọ eleyii lasiko to lọ ṣabẹwo si awọn ẹbi Kashamu lẹyin to doloogbe.

Gomina ni botilẹ jẹ pe àwọn ko jọ si ninu ẹgbẹ oṣelu kan naa, sibẹ oun mọ pe sẹnetọ naa ti ran awọn eniyan lọwọ gidigidi.

O ni ọrẹ oun ni oloogbe botilẹ jẹ pe alatako oun ni lasiko idibo gomina lọdun 2019.

Abiodun ba iyawo oloogbe Susan Buruji-Kashamu ati awọn ẹbi, to fi mọ gbogbo ọmọ bibi ilu Ijebu-Igbo kẹdun lori iku ilumọọka naa.

Bakan naa lo gbadura ki Ọlọrun tẹ ẹ si afẹfẹ rere.

Wo bi wọ́n ṣe sìnkú Kashamu ní Ijebu-Igbo

Wọ́n ti pari eto sin òkú sẹnatọ nígbà kan ri Buruji Kashamu tí wọ káà ilẹ̀ sún ni ìlú rẹ̀ ni Ijebu-Igbo.

Sáájú ní Gómìnà ìpínlẹ̀ Ogun, dapo Abiodun ti ṣàbẹ̀wò si ilú Ijebu-Igbo to jẹ́ ìlú olóògbèé.

Àwọn ọ̀rẹ́ olóògbèé, àwọn abánikẹ́dùn àti ọ̀pọ̀ àwọn olóṣèlú ló péjú síbi ìsìnkú náà.

Ẹ̀wẹ̀, ó jọ bí ẹni pé, àwọn ènìyàn tó péjú síbi ètò ìsìnkú náà ko tẹ̀lé ìlànà ìjìnà síraẹni.

Buruji Kashamu: Olusegun Obasanjo ní ohun tí òun sọ nípa Kashamu lẹ́yìn ikú rẹ̀ kìí ṣe àṣìsọ

Aarẹ Naijiria nigba kan ri, Oluṣegun Obasanjo ti sọ pe oun ko ṣi sọ ninu atẹjade ti oun fi lede lẹyin iku Sẹnatọ to n ṣoju ẹkun idibo ila oorun ipinlẹ Ogun tẹlẹ, Buruji Kashamu.

Agbẹnusọ Obasanjo, Kehinde Akinyemi, lo fidi ọrọ naa mulẹ ninu ifọrọwerọ pẹlu BBC Yoruba.

O ni ohun to ba wu onikaluku lo le sọ nipa erongba rẹ lori iṣẹlẹ iku Kashamu ni eyi to fihan pe ohun to wu Aarẹ Obasanjo naa lo sọ sita ninu ero tirẹ.

Ogbeni Kehinde sọrọ lori ikini akọni ti Obasanjọ fun oloogbe Kashamu ati pe, Obasanjọ fi ibanujẹ rẹ han lori iku naa pẹlu adura pe ki Olorun tẹ oloogbe si afẹfẹ rere ninu atẹjade kan naa.

O ni erongba Obasanjo ni ọrọ to wa ni ninu atẹjade naa, ati pe gẹgẹ bi ọmọ Naijiria, Baba Iyabo lẹtọọ lati sọrọ labẹ ofin.

Kini ero rẹ lori awọn to n bẹnu atẹ lu ọrọ Obasanjọ lori ayelujara?

Ni ti awọn to n bu ẹnu atẹ lu Obasanjo lori atẹjade ọhun, Akinyemi sọ pe gbogbo eeyan lo lẹtọọ lati sọ erongba inu wọn.

O ni nitori naa bi aarẹ ana ọhun ṣe le e sọrọ ni awọn eeyan ọhun naa ni ẹtọ lati sọ tinu wọn.

Akinyemi sọ pe Baba Iyabo ko kabamọ ọrọ to sọ ninu atẹjade naa.

Ohun ti Obasanjo sọ ninu atẹjade ọhun to da awuyewuye silẹ ni pe "Buruji lo gbogbo ọgbọn alumọkọrọyi inu ofin lati bori awọn ẹsun ọdaran ti wọn fi kan an ni Naijiria ati loke okun, ṣugbọn ko le e sa mọ iku lọwọ."

Kini awọn ọmọ Naijiria bii Fayooṣe ati Imo Ugochinyere ti sọ?

Ṣugbọn ọpọ awọn ọmọ Naijiria lo ti bẹrẹ si n sọ ero wọn lẹyin ti atẹjade ọhun jade lori ayelujara, bi awọn kan ṣe n sọ pe ootọ ni Obasanjo sọ, lawọn mi n sọ pe agbalagba kii sọrọ tan lẹnu.

Lara awọn to da si ọrọ naa ni Gomina ipinlẹ Ekiti tẹlẹ, Ayodele Fayose to sọ pe, iba ti dara ki Obasanjo sọ ọrọ to sọ lẹyin iku Kshamu lọju rẹ nigba to ṣi wa lori oke eepẹ.

Ikenga Imo Ugochinyere ni tirẹ gboriyin fun Obasanjọ pe o sọju abẹ niko lori ọrọ naa lai parọ nitori oloogbe Kashamu.

O parọwa fun ẹnikẹni to ba fẹ gbọ ootọ ọrọ to n fọnrere iwa akin oun lẹyin iku rẹ pe ko ṣe rere lori oke eepẹ ko to ku.

Folarin Ademola sọ pe Obasanjo ko sọ pe oun naa ko da ẹṣẹ ri, ṣugbọn ti eeyan ba ri ootọ o yẹ ko le e sọ.

Dokita Dipo Awojide ni tirẹ ni pẹlu ọrọ ti Obasanjo sọ, sẹ lo dabi ẹni pe baba ko ni ẹmi idariji latari ohun to ti ṣelẹ sẹyin laarin rẹ ati Kashamu.

Ni ti Wale Adetona, o ni to ba jẹ pe Obasanjo lo kọ atẹjade naa, ohun to wa lọkan rẹ lo sọ nipa Kashamu, ko si yẹ ki awọn binu si ọrọ naa.

Ẹ wo oun ti awọn ọmọ Naijiria miran sọ lori atẹjade ọhun.

Buruji Kashamu: Wo díẹ̀ lára ohun tí Senato Buruji gbé ilé ayé ṣe kí ọlọ́jọ́ tó dé

Ta ni Buruji Kashamu?

A bi Kashamu ni ipinlẹ Ogun ni ẹkun guusu iwọ oorun Naijiria lọjọ kọkandinlogun, oṣu karun un, ọdun 1958.

O lọ sile ile iwe alakọbẹrẹ Ansarudeen ni Ijẹbu Igbo ko to o kuro nibẹ lọdun 1972 lọ pari iwe rẹ ni St John Modern School ni ipinlẹ Eko.

Lẹyin eyi lo lọ sile ẹkọ aṣalẹ ti Igbobi College nigba ti o n ṣiṣẹ lojumọmọ.

Bo ṣe pari nibi lo ni anfani lati lọ si Pitman College ni London ni ibi to ti kọ nipa amojuto oko owo ṣiṣe.

Cambridge Graduate University ni Massachusetts fun Kashamu ni oye ifidanilọla ti ọmọwe ninu eto akanse ti wọn ṣe fun un ni ipinlẹ Eko.

Lọdun 1998 ni wọn mu Kashamu ni ilu Oba ni United Kingdom lori ẹsun to nii ṣe pẹlu egbogi oloro ati owo to to $230, 000 to fẹ ko wọ ilu lọna aitọ, ki wọn to tuu silẹ lọdun 2003.

Buruji Kashamu ninu Iṣelu:

Buruji Kashamu kopa pupọ ninu oṣelu ipinlẹ Ogun

O jẹ agba ẹgbẹ ati Oloye ẹgbẹ ninuẹgbẹ oṣelu PDP ni ipinlẹ Ogun to wa ni Guusu iwọ oorun Naijiria.

O dije dupo aṣojuṣofin, o si wọle lati ṣoju awọn eniyan ẹkun ila oorun ipinlẹ Ogun nibi to ti ni ibo 99, 540 lati bori akẹgbẹ rẹ ti wọn jọ dije dupo.

Koda, o ṣe alaga igbimọ tẹẹkoto fun gbogbo ẹgbẹ oṣelu PDP ni Guusu iwọ oorun Naijiria patapata nigba kan.

Lọdun 2018 ni wọn yọ ọwọ kilanko Kashamu kuro ni ẹgbẹ oṣelu PDP ko to gba ile ẹjọ lọ ni Abuja ti wọn si yi i pada loṣu kẹwaa, ọdun 2018.

O dije dupo gomina fun ipinlẹ Ogun labẹ asia PDP lọdun 2019 ko to padanu ti Dapọ Abiodun ti APC si wọle gẹgẹ bii gomina ipinlẹ Ogun.

Koda, ipo kẹrin lo ṣe ninu idibo gomina naa nipinlẹ Ogun.

Buruji Kashamu ti tẹ́rí gbasọ

Senatọ tó n sojú ẹkùn Ogun East nígbà kan rí, Buruji Kasahamu ti jẹ́ Ọlọrun nípe.

Gẹ́gẹ́ bi ìlúmọ̀ọ́ka oloṣèlu Ben Murray-Bruce ṣe sọ, O ni ó kú si ilé ìwòsàn First Cardilogy Consultant ni ilú Eko.

Bruce ni ọ̀rẹ́ wọléwọde ni òun àti Kasamu kó tó jẹ́ Ọlọrun nípè.

Sááju àsìkò yìí ni ìròyìn ti kan pé Kasamu wá ni ẹsẹ̀ kan ayé, ẹsẹ̀ kan ọrún nítori àwọn ààrùn míràn ti Coronavirus bá lára rẹ̀.

Buruji kú lẹ́ni ọdún méjìlélọ́gọta

Ní kété ti òkìkí ikú Kasamu kan, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Naijiria lo ti n ṣelédè lẹ́yin rẹ̀.

Díẹ̀ nínú ǹkan ti àwọn ènìyàn ń sọ rèé.

Àwọn ọ̀rẹ́ àti ojúlùmọ̀ tó n ṣelédè lẹ́yìn rẹ̀