Osun State Elections: Ilé ẹjọ́ sún ìgbẹ́jọ́ Adeleke síwájú

Ile ẹjọ ti wọn ti gbẹjọ oludije ipo gomina nipinlẹ Oṣun labẹ asia ẹgbẹ oṣelu PDP, Sẹnetọ Ademọla Adeleke ti sun ẹjọ rẹ siwaju di ọjọ kẹrinlelogun oṣu kẹfa ọdun 2019.
Lonii ni Oludije fun ipo gomina ipinlẹ Oṣun labẹ asia ẹgbẹ oṣelu PDP ninu idibo ọdun 2018, Sẹnetọ Ademọla Adeleke ti foju ba ile ẹjọ Majisireti to wa ni Mpape l'Abuja.
Olugbaninimran fun sẹnetọ Adeleke ba BBC Yoruba sọrọ.
Ile iṣẹ ọlọpaa fi ẹsun marun ọtọọtọ kan an. Si eyi, sẹnetọ Adeleke ni ohun ko jẹbi awọn ẹsun naa ti adajọ Mohd Zubairu si gba beeli rẹ pẹlu iye owo miliọnu meji naira ati pipese oniduro kan bakan naa. Alukoro ile iṣẹ ọlọpaa, Frank Mba lo fi ọrọ yii lede pe wọn gbe sẹnetọ naa si atimọle lori ẹsun to nii ṣe pẹlu lilo ayederu iwe ẹri.
Ẹwẹ, awọn oniroyin to fọrọ wa a lẹnu wo ni ko sọ pato awọn ẹsun ti wọn ka si i lẹsẹ.
Lọjọ aje, ẹgbẹ oṣelu PDP fẹsun kan pe wọn n pete lati fun Adeleke ni majele ni.
Gẹgẹ bi wọn ṣe sọ ọ, ana ni PDP ní Ọlọ́pàá ti mú Sẹ́nétọ̀ Ademọla Adeleke sí àhámọ́ latari ọrọ ti ẹgbẹ ṣapejuwe gẹgẹ bii "aibọwọ fun alakalẹ ofin ile ẹjọ giga".









