Ogun Primary: Ogunbanjo ni yóò dupò gómìna f'ẹ́gbẹ́ ANN

awọn oludije
Àkọlé àwòrán, Egbe oṣelu ANN kéde àwọn oludije idibo 2019

Ademola Olalekan Ogunbanjo ni yoo dije fun ipo gomina nipinlẹ Ogun labẹ asia ẹgbẹ oṣelu Alliance for New Nigeria, ANN ninu idibo ọdun 2019 .

Ọjọbọ, ọjọ kẹrin, osu kẹwaa ni ẹgbẹ ANN kede Ogunbanjo pe oun lo jawe olubori ninu idibo abẹle to waye nilu Abeokuta lẹyin ti awọn meji ti wọn fẹ jọ figagbaga tẹlẹ yẹba fun un.

ludije
Àkọlé àwòrán, Ogunbanjo gba pe ife awon ara ilu loun ni lokan lati le koju enikeni ti won yoo jo dije ni 2019

Ọpọlọpọ awọn oludibo to jẹ ọmọ ẹgbẹ lọ jade wa yan ẹni to wu wọnlati ṣoju wọn ninu idibo 2019 sile igbimọ aṣofin ati gomina ni gbongan Centenary ni Ake nilu Abeokuta.

Awọn ọdọ lo pọ ninu ẹgbẹ ANN, inu ẹgbẹ yii kannaa ni illumọka agbaninimọran Fẹla Durutoye ti jawe olubori gẹgẹ bi ẹni ti yoo dupo Aarẹ orilẹede Naijiria labẹ asia ẹgbẹ ANN ninu idibo ọdun 2019.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ẹgbẹ oṣelu ANN kede Durotoye gẹgẹ bi oludije fun ipo Aarẹ labẹ asia ẹgbẹ ọhun lọjọ kọkandinlọgbọn, osu kẹsan an to kọja.

Fela Durotoye

Oríṣun àwòrán, Twitter/@feladurotoye

Àkọlé àwòrán, Fela Durotoye ṣetán láti dupò Ààrẹ orílẹ́èdè Nàìjírìa

Diẹ lara awọn ti yoo dije fun ipo kan tabi omiran ninu ẹgbẹ ANN ninu idibo ọdun 2019 ni wọnyii.

Àwọn olùdíje lábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú ANN

Oríṣun àwòrán, ANN

Àkọlé àwòrán, Àwọn ọ̀dọ́ tí wọ́n fẹ́ díje nínú ìdìbò gbogbogbò ọdún 2019

Ẹ o ranti pe Durotoye ati ẹgbẹ ANN wa lara awọn ti o n ṣe ipolongo pe ki awọn ọdọ wa lara awọn to n ṣe ijọba orilẹ-ede Naijiria.

Àkọlé fídíò, 'Obinrin jẹ amuludun'
Àkọlé fídíò, Àwa obìnrin tó ń lépa afòjúsùn máa n ba ọkùnrin lẹ́rù ni -Toyin Lawani