You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Odunlade Adekola: Wo Aàmì èye tí Odunlade Adekola gbà ní AMVCA
Gbajugbaja oṣere tiata Nollywood to tun n gbe awo orin jade, Odunlade Adekọla ti gba ami ẹyẹ oṣere tiata ọkunrin to pegede julọ ni agbo oṣere.
Odunlade bori awọn oṣere to kopa ninu fiimu Rattle Snake, Amina, Gold Coast Lounge ati awọn miran lati gba ami ẹyẹ naa.
Ami ẹyẹ AMVCA ni wọn ma n fun awọn oṣere fiimu, awọn ti wọn jọ ṣe fiimu ati gbogbo awọn ti wọn jọ kopa ninu ẹ.
- Yorùbá ẹ fúnra, àwọn tó ṣekú pa Deborah fẹ́ dá ògún sílẹ̀ ni, wọn kò gbọdọ̀ lọ láì jìyà -Gani Adams
- Láti ìgbà tí wọ́n ti bí mi, kò sí obìnrin tí mo kọnu ìfẹ́ sí tí kò gbà fún mi -Efuoma Amos
- Wo àwọn órílẹ̀èdè mẹ́wàá ti ojú ọjọ́ wọn tí n gbóná jan-jan ju ti tẹ́lẹ̀ lọ
- Àwọn ọlọ́kadà dáná sun 'Sound engineer' l'Eko lẹ́yìn àríyànjiyàn lórí ₦100
- Wo àwon ìròyìn òfégè nípa ikú Deborah Ṣamuel àti ìkọlù sí Bishop Kukah
- Àwọn Mùsùlùmí tó ṣekúpa Deborah nítori ọ̀rọ̀ ẹ̀sìn kò ní wọ párádísè - Sheikh Gumi
- Tọkọtaya gbé ọmọ wọn lọ sílé ẹjọ́ torí àì bímọ lẹ́yìn ìgbéyàwó
- Kà nípa àwọn mínísítà mẹ́wàá tó kọ̀wé fipò sílẹ̀ lábẹ ìjọba Ààrẹ Buhari
- Àwọn àgbébọn ti tú olóyún tó wà lára àwọn awakọ̀ reluwé Abuja sí Kaduna tí wọ́n jí gbé sílẹ̀
- Bóo bá ma ń la ẹnu kalẹ̀ lójú oorun, wo ìpèníjà tí o lè ní
Lara awọn akẹgbẹ rẹ to gboriyin fun Adekola ni Bukunmi Oluwashina to ṣe fiimu ''Jankariwo'' to fi gba ami ẹyẹ.
Bukunmi lasiko to n gboriyin fun akẹgbẹ rẹ ni o jẹ moriya fun oun.
Bakan naa lo dupẹ lọwọ oṣerekunrin naa ti oun pe si fiimu oun to si da loun nipa fiimu rẹ ''Jankariwo'''.
''A ṣe aṣeyọri lori fiimu Jankariwo. Iwuri nla lo jẹ fun mi bi wọn ṣe darukọ fiimu mi fun igba meji ni ami ẹyẹ to gajulọ ni ilẹ Afrika.
''Ẹ ku oriire ẹgbọn mi, ti mo n pe ni ''Number 1"', ẹ se ti ẹ jẹ iwurii ninu iṣẹ ti ẹ yan laayo.''
Bakan naa ni Bukunmi dupẹ pe o gbọ ipe oun lori fiimu naa, to si gboriyin fun pe iṣẹ nla to ṣe.
''Mo dupẹ lọwọ awọn to bami ṣiṣẹ naa ti wọn si jẹ ko ṣe aṣeyọri.''
Fiimu naa gba ami ẹyẹ gẹgẹ bi fiimu Yoruba akọkọ ti wọn yoo fi orukọ rẹ lede fun ami ẹyẹ ni ọna meji.
Ami ẹyẹ Ilẹ Africa ti ''Africa Magic Viewers'Choice Awards (AMVCA), waye ni Ọjọ Kẹrinla, Oṣu Karun un, 2022.
Ami ẹyẹ naa ni awọn kan ma n pe ni ami ẹyẹ ti Oscar ti ilẹ Afrika, ti wọn ti n fun awọn oṣere fiimu, awọn to n gbe wọn jade ati awọn onimọ miran ni ẹka wọn.
Ọdun yii ni ami ẹyẹ naa tun pada si ilẹ Afrika lẹyin ti wọn ko lee ṣe ni ọdun to kọja nitori ajakalẹ aarun Coronavirus.