You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Sunday Igboho: Okei-Odumakin ké sí ìjọba Benin Republic látí fí Sunday Igboho silẹ̀ kó lé é gba Germany lọ
Gbajugbaja ajafẹtọ ọmọniyan ati aarẹ Women Arise Centre for Change, Joe Odumakin ti kesi ijọba orilẹede Benin Republic lati fi Sunday Igboho silẹ ni waranṣeṣa.
Odumakin ninu atẹjade to fi lede ni ki awọn eniyan sọra fun iroyin ẹlẹjẹ nipa Sunday Igboho nitori o le dena gbogbo eto ti wọn n ṣe lati gba itusilẹ rẹ.
O ni igbagbọ oun ni pe ijọba Benin Republic jẹ ijọba to bọwọ fun ofin ọmọniyan, to si n tẹlẹ aṣẹ eto ijọba tiwantiwa, nitori naa ki wọn tete mura si ibeere Sunday Igboho fun ominira ni orilẹede miran lati sa asala fun ẹmi rẹ.
- 'Sunday Igboho kò yojú sílé ẹjọ́ ní Cotonou, àtìmọ́lé ló ṣì wà'
- Ọ̀rọ̀ tí Oluwo sọ ní Yidi Ileya pé ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Igboho kò kan òun, kò dára rárá - Olùwọ́de
- Sunday Igboho kìí ṣe ‘Terrorist’, ẹ fi sílẹ̀ ní àhámọ́ - Àwọn Olùwọ́de faraya
- "A kò sinmi lórí ọ̀rọ̀ Yoruba Nation, Sept 14 lá yọjú sí United Nation"
- Ooni Ife àtàwọn èèkàn Yorùbá ṣèpàdé ìdákọ́nkọ̀ lórí ọ̀rọ̀ Sunday Igboho
- Wọn yóò tẹ ẹ̀tọ́ Sunday Igboho mọ́lẹ̀ tó bá padà sí Nàìjíríà - Afenifere Renewal Group
- "Ìdí tí ìjọba Benin Republic kò ṣe ní le è fa Igboho lé Nàíjíríà lọ́wọ́ ree"
- "Ẹ̀yìn ọba Yorùbá, ẹ dìde láti gbe Sunday Igboho níjà kó le jàré nílẹ̀ Benin"
'' Kii ṣe aimọ fun oloko wi pe ijọba Naijiria ko ni ayọle, ti wọn si le e tẹ oju ẹtọ Sunday Igboho mọlẹ, ti o ba pada wa si Naijiria.''
''Orilẹede Naijiria ti ko ri nkan ṣe si ikọ Boko Haram ati awọn agbebọn to n ba nkan jẹ ni Naijiria to si n pa awọn araalu, amọ awọn ajijagbara to n beere fun ẹtọ wọn ni ijọba fẹ ma a gbogun ti''
''Apẹrẹ ni bi wọn ṣe lọ mu Nnamdi Kanu lọna ti ko ba ofin mu, ti wọn si n bo gbogbo rẹ mọlẹ lai jẹ ki ẹnikẹni yoju si''
Eleyii ko dara to nitori ẹtọ ọmọniyan ni lati ni anfaani si igbeaye to rọrun ati alaafia to fi mọ eto aabo to gbooro fun awọn eniyan.
Odumakin ni o ṣeni laanu pe ijọba Naijiria fi eyi silẹ, ti wọn si n le ohun ti ko si kiri, eleyii ti yoo jasi opin orilẹede Naijiria ti ijọba ba n ba bayii lọ.
Buhari, tú Sunday Igboho sílẹ̀ bo ṣe tú Boko Haram tó ronúpíwàda sílẹ̀ - Ladoja
Gomina tẹlẹri nipinlẹ Oyo, Sẹnetọ Rasidi Adewolu Ladoja ti sọ wi pe, ijọba apapọ lo da awọn ajijagbara bii Sunday Igboho, to n ja fun ilẹ Yoruba ati Nnamdi Kanu to n ja fun idasilẹ orilẹede Biafra silẹ.
Ladoja lo sọ bẹẹ ni ile rẹ lasiko to n ba awọn akọroyin sọrọ lẹyin to gbadura Ileya tan ni ọjọ Iṣẹgun.
Ladoja to tun di ipo Osi Olubadan ti ilu Ibadan mu lo fesi si iroyin pe ọwọ awọn agbofinro lorilẹede Naijiria ti tẹ Sunday Igboho ni ilu Cotonou, lorilẹede Benin Republic.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Àwọn agbẹjọ́rò tó dáńtọ́ ti wà ní Cotonou láti gba ìdáǹdé Sunday Igboho - Akitoye
- Wo ìgbà márùn-ún tí wọn saáyan láti mú Sunday Igboho
- Wo àwọn ìgbésẹ̀ tí Sunday Igboho gbé, tó fi di ọ̀tá ìjọba
- Ṣé lóòtọ́ ni ìjọba Naijiria ti fi pampẹ̀ òfin mú Sunday Igboho?
- "Á dá ohun àlùmọ́ọ́nì wa jọ láti gbèjà Sunday Igboho nílé ẹjọ́"
- "Buhari, kí ló dé tó ń mu Sunday Igboho àti Kanu, amọ́ tó mu àwọn agbébọn?"
- Èémọ̀! Pásítọ̀ dèrò ọ̀run níbi tó tí ń l'àjà láàrin ọkọ àti ìyàwó- Iléeṣẹ ọlọ́pàá
O ni ijọba apapọ to kọ lati koju awọn ipenija ijinigbe, ipaniyan awọn araalu kaakiri orilẹede Naijiria, paapaa ilẹ Yoruba lo mu awọn eniyan bi Sunday Igboho di adari fun awọn eniyan rẹ.
Gomina ipinlẹ Oyo tẹlẹ wa parọwa si ijọba apapọ lati ṣe pẹlẹpẹlẹ pẹlu bi wọn ṣe fi panpẹ ọba mu Sunday Igboho nitori ọpọlọpọ eniyan bii Sunday Igboho ni yoo dide ti ijọba ba fi ọwọ agbara mu awọn ti wọn mu yii.
''Awọn eniyan bẹrẹ si ni ja fun ara wọn nitori ijọba kuna lati da abo bo awọn araalu, ti wọn si kesi awọn to le e ja fun wọn lati wa ran wọn lọwọ''
Kii ṣe pe wọn fi panpẹ ọba mu Sunday Igboho lo jẹ mi logun, bi ko ṣe wi pe ijọba apapọ gan an lo lẹbi ọrọ yii nitori awọn lo jẹ ki iru awọn eniyan bayii dide.
Ẹ wo iru ipaniyan to waye ni ilu Igangan ati awọn agbegbe miran. Awọn wọn yii yoo sọ wi pe awọn ni baba iṣalẹ kan, ti wọn yoo si fi wọn silẹ.''
Awọn Fulani darandaran ti pa ọpọlọpọ eniyan, ti ninu wọn si jẹ Dokita Fatai Aborode, Alhaji Sherifat Adisa, ti ijọba ko si fi panpẹ ọba mu ẹnikẹni.''
''Nitori awọn eniyan bayii ni Sunday Igboho ṣe bẹrẹ si ni ja fun awọn eniyan rẹ, to si di ẹni ti wọn n bu ọla fun kaakiri.''
''Ti wọn ba mu Sunday Igboho loni, ti ijọba si kọ lati kọ ibi ara si ipenija eto aabo to mẹhẹ yii, awọn eniyan bii Sunday Igboho yoo dide''
''Ko bajẹ to eleyii ri, o si ṣeni laanu pe aarẹ Muhammadu Buhari ko kọbi ara si awọn ipenija yii.''
''Bii Kanu, Sunday Igboho ti jẹ adari fun awn eniyan kan, eleyii to yẹ ki ijọba apapọ ṣe jẹjẹ lori ọrọ yii''
Bakan naa ni Gomina tẹlẹri nipinlẹ Oyo naa gba ijọba apapọ ni imoran lati tu Sunday Igboho, Nnamdi Kanu silẹ bii wọn ṣe tu awọn ikọ agbesunmọmi Boko Haram silẹ nitori wọn ronu[piwada.
Rashidi Ladoja fikun pe ijọba mu awọn agbesunmọmi Boko Haram kan ni ọdun to kọja ti wọn si tu wọn silẹ fun ijọba ipinlẹ Borno, nitori naa ki wọn se bẹẹ fun Sunday Igboho ati Nnamdi Kanu.