NGA vs RSA: 'Bode Thomas' àti àwọn àṣà mííràn tó jẹyọ nínú ìdíje AFCON

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Igbakiigba ti ọrọ ba ti pa Naijiria ati South Afrika pọ,bi igba pe wọn jọ fẹ doju ija kọ ara wọn ni o maa n jẹ.

Lori papa ere bọọlu papa julọ, wọn kii fi oju ọrẹ wo ara wọn tabi ọmọ ilẹ adulawọ kanna.

Awọn mejeeji fi ifigagbagba yi han nigba ti Naijiria ati South Afrika pade ninu idije AFCON 2019

Naijiria bori South Afrika pẹlu ami ayo meji sookan ti o si tumọ si pe wọn yoo tẹ siwaju lọ abala to kangun si aṣekagba.

Loju opo Twitter ati Facebook, iroyin aṣeyọri Naijiria ti mu ki awọn ọmọ ile naa ati awọn akẹgbẹ wọn lati South Afrika ma fọrọwerọ.

Nibi ọrọ yi ni awọn aṣa kan ti jẹyo eleyi ti o gba ori ayelujara kan.

Bode Thomas

Ọmọ Yoruba to ba n gbe ilu Eko yoo ti gbọ orukọ Bode Thomas ri.

Opopona kan nilu Eko lo n jẹ Bode Thomas lagbegbe Surulere amọ lẹyin ti Naijiria fi ẹyin South Afrika janlẹ, o gba itumọ miiran

Awọn Iroyin ti ẹ le nifẹ si

Lati oju opo Twitter, diẹ lara awọn itunmọ tuntun ti awọn eeyan fun orukọ yi re e:

Lotitọ ati ododo, ọtọ ni nnkan ti olorin to kọrin rẹ jẹjẹ sọ ninu orin ti awọn ọmọ Naijiria yi itumọ rẹ pada si Bode Thomas.

T'oun ti pe wọn mọ itunmọ rẹ, awọn ọmọ Naijiria ni ko kan awọn nitoripe asiko ree fawọn lati fi South Afrika ṣe yẹyẹ.

Xenophobia

Idẹyẹ si awọn ọmọ Naijiria lati ọwọ awọn eeyan South Afrika kan ko jẹ tuntun mọ.

Amọ bayii ti Naijiria ti gbewuro soju South Afrika, nnkan ti yi pada ti awọn ọmọ Naijiria si ni asiko to bayi ki awọn naa ṣe idẹyẹ si sawọn ọmọ Naijiria.

Samuel Chukwueze ẹlẹsẹ ayo to ge awọn ọmọ South Afrika lori papa ni wọn ni o n bawọn deye si South Afrika pada

Ossai Joshua tilẹ ni Super Eagles fi aṣeyọri wọn ninu ifẹsẹwọnsẹ naa jẹ ogede South Afrika ni.

Lakotan gbogbo awọn nkan ti awọn eeyan n sọ ko ju ere lọ irufẹ eleyi ti o ma n waye laarin awọn alatilẹyin ere boolu jakejado agbaye.