You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Ẹgbẹ́ agbésùnmọ̀mí tuntun ti wọ Naijiria, wọ́n sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ń ṣọsẹ́ – Iléeṣẹ́ ọmọ ogun
Ileeṣẹ ọmọ ogun Naijiria ti kede pe ẹgbẹ agbesumọmi miran ti n ṣọṣẹ ni Naijiria.
Orukọ ẹgbẹ naa ni wọn pe ni ‘Lukarawas.’
Ileeṣẹ ologun ni, agbegbe Sokoto ati Kebbi ni wọn ti n ṣọṣẹ lọwọ yii.
Nigba to n ba awọn akọroyin sọrọ l’Abuja, agbẹnusọ ileeṣẹ ọmọ ogun Naijiria, Edward Buba sọ pe, awọn ọmọ ogun ti n kọju ija si awọn agbesumọmi ọhun.
O ni “Awọn ọmọ ogun ti n koju ẹgbẹ agbesumọmi tuntun ni iwọ oorun ariwa.
“Orukọ ẹgbẹ naa ni Lukawaras, wọn si ti n ṣiṣẹ papọ pẹlu awọn agbesumọmi lagbegbe Sahel ti wọn wa lati Mali ati Niger Republic.”
“Wọn ti bẹrẹ si n yọ kẹlẹ wọ agbegbe ariwa Naijiria, paapaa ipinlẹ Sokoto ati Kebbi. ”
O fi kun pe ẹgbẹ naa lo ṣokunfa idaduro iṣẹ to waye laarin ileeṣẹ ọmọ ogun Naijiria ati orilẹede Niger.
Ẹwẹ, ileeṣẹ naa ti kede pe oun n wa awọn ọmọ ẹgbẹ agbesumọmi mẹsan an kan fun ipa ti wọn ko ninu dida omi alaafia Naijiria ru.