You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Wo àwọn èèkàn ìlú tí ayé ti pa irọ́ ikú mọ́ nígbà tí wọ́n ṣì wà láyé
Ikede ipapoda eeyan nilẹ Yoruba kii ṣe ohun ti a n fi ikanju tabi awada ṣe rara. Kodaa, o loju ẹni ti o le tufọ ijadelaye ẹlomii, nitori awọn agba nikan lo mọ ọna ti wọn gbee gbaa ti ijaya ikede iku ẹnikan ko fi ṣekupa ẹlomii.
Ṣugbọn ifilọlẹ itakun agbaye to fun gbogbo eniyan lanfani lati fi ọrọ lede lori ayelujara ti ṣe akoba fun pupọ ninu awọn aṣa ti a de aye ba.
L'ọpọlọpọ igba ni awọn eeyan maa n kede nnkan toju wọn ko to lori ayelujara lai ṣe iṣẹ iwadii to kuna.
Lara awọn iroyin ofege to n ti ipa ẹsẹ eyii waye ni ki a kede wi pe ẹnikan ti jade laye nigba ti wọn ṣi wa laaye.
Wo diẹ lara awọn olokiki ti awọn eeyan fi iroyin ofege parọ iku mọ:
1. Ọbafẹmi Awolọwọ;
Oguna gbongbo oloṣelu, Ọbafẹmi Awolọwọ jade laye lọjọ kẹsan an oṣu kaarun ọdun 1987 lẹni ọdun mejidinlọgọrin, ṣugbọn ki o to papoda ni ọpọlọpọ iroyin ofege ti n fo kaakiri pe Awolọwọ ti di oloogbe.
Lẹyin ti Awolọwọ tun jade tan, ọpọ awuyewuye tun rọ mọ iru iku to gbẹmi rẹ. Bi awọn kan ṣe n sọ wi pe ninu baluwẹ nibi to ti n fọ'yin ni ọlọjọ ti de, ni ọpọ iwe itan mii tun tọka rẹ wi pe niṣe lo gba ẹmi ara rẹ nipa jijẹ majele nitori rogbodiyan to niiṣe pẹlu eto oṣelu orilẹede yii l'ọdun naa lọhun.
2. Ernest Shonekan;
Adele alaṣẹ orilẹede Naijiria tẹlẹri, Oloye Ernest Adegunle Oladeinde Shonekan jade laye lọjọ kọkanla, oṣu kini ọdun 2022 lẹni ọdun marundinlaadọrun. Lati nnkan bii ọdun meji saaju ipapoda rẹ ni ọkanojọkan iroyin ofege ti n fo kaakiri ayelujara wi pe amofin ati asaaju ilu naa ti jẹ Ọlọrun ni ipe.
Lara awọn to fi ọrọ lede lati koro oju si iru iroyin ofege bẹẹ ni ijọba ipinlẹ Ogun, Alake ti ilẹ Ẹgba, Oba Adedotun Gbadebo.
3. Abiọla Ajimọbi;
Oloogbe Sẹnẹtọ Abiọla Ajimọbi ti o jẹ Gomina tẹlẹri fun ọdun mẹjọ gbako n'ipinlẹ Ọyọ lugbadi aarun Korona, Covid-19 l'ọdun 2020, eyii lo si ṣe okunfa ipapoda rẹ.
Lasiko ti Ajimọbi ṣi wa nile iwosan kan ti o ti n gba itọju nilu Eko, ọpọlọpọ ijaya lo ba mọlẹbi ati awọn ololufẹ rẹ n'ipasẹ awọn oriṣiriṣi iroyin ofege to kede iku rẹ lọjọ aipe.
Awọn alabṣiṣẹ pọ rẹ, mọlebi ati aya ọmọ rẹ kan wa lara awọn to jiyan iroyin naa, ki to di pe ọlọjọ de ba Ajimọbi lọjọ kẹẹdọgbọn, oṣu kẹfa ọdun 2020 lẹni aadọrin ọdun.
Awọn olokiki kan ṣi wa laaye titi di ọjọ oni to jẹ wi pe a ti gbọ iroyin ofege nipa ipapoda wọn sẹyin.
Lara wọn ni:
1. Ibrahim Badamasi Babanigida
A bi aarẹ ologun orilẹede Naijiria tẹlẹri, Ibrahim Babangida lọjọ kẹtadinlogun oṣu kẹjọ ọdun 1941, l'ayọ ati alaafia lo si wa nluu Minna, n'ipinlẹ Niger nibi ti o fi ṣe ibugbe. Lara awọn eeyan ti a ti gbọ iroyin ofege nipa iku wọn daadaa ni Babangida.
Ninu oṣu kẹfa ọdun 2016, Babangiga lọ ṣe ayẹwo ilera rẹ lorilẹede Germany fun ọsẹ mẹta. Ki o to de pada ni iroyin gbode wi pe o ti jade laye, ṣugbọn irọ lasan ni.
Bakan naa ninu oṣu kejila ọdun 2019, iroyin mii ti lu gbogbo ori ayelujara pa wi pe Babangida ti papoda. Agbẹnusọ rẹ, Kassim Afegbua lo jade sita ko si iku loju ọga oun o.
Nigba ti yoo fi di inu oṣu kini ọdun 2022, iroyin ofege mii to jade wi pe Babangida ti re ibi agba n ree, ṣugbọn irọ lasan bansa ni.
2. Olu Jacobs
Gbajugba oṣere tiata, Olu Jacobs naa ko gbẹyin lara awọn ti o ti foju wina iroyin ofege nipa iku aitọjọ.
A bi Jacobs ni ọjọ kini, oṣu keje ọdun 1942 n'ipinlẹ Ogun.
Botilẹ jẹ wi pe ẹni ọdun mọkanlelọgorin naa n ṣe aisan lẹnu ọjọ mẹta yii, o ṣi n bẹ laye titi di asiko yii.
Ninu oṣu kẹjọ ọdun 2022 ni iroyin ofege kan lu sita wi pe gbajugbaja oṣere naa ti jade laye, ṣugbọn aya rẹ ti o jẹ gbajugbaja oṣere tiata bakan naa, Joke Silva ni iro lasan ni iroyin naa.
3. Mohammadu Buhari
Aarẹ ana lorilẹede Naijira, Mohammadu Buhari n bẹ lara awọn eeyan ti awọn oniroyin ofege ti kede iku wọn l'ọpọ igba.
Kodaa, wọn tun sọ ti Buhari de ibi pe arakunrin kan ti wọn pe orukọ rẹ ni Jubril lati orilẹede Sudan lo gbe aawọ Buhari wọ lẹyin ti o jade laye.
A bi Buhari lọjọ kẹtadinlogun oṣu kejila ọdun 1942 n'ipinlẹ Katsina.
Lasiko ti o wa lori apere ijọba gẹgẹ bi aarẹ orilẹede Naijiria, ọpọlọpọ igba lo rin irinajo lo si oke okun fun itọju ilera. Asiko kan wa ti Buhari rin irinajo fun oṣu mẹta gbako lati lọ gba itọju ilera, eyii lo mu ki o rọrun fun iroyin ofege lati maa fo kiri wi pe aarẹ orilẹede Naijiria nigba naa ti di ẹni ilẹ.
Ninu oṣu kaarun ọdun 2017, iroyin ofege kan gbode wi pe Buhari ti jade laye niluu London nibi ti o ti lọ gba itọju ilera, ṣugbọn irọ lasan ni.
Nigba ti yoo fi di inu oṣu kejila ọdun 2018, iroyin mii tun jade nipa ipapoda rẹ, ṣugbọn ko si ootọ kankan nibẹ.
Awọn oniroyin ofege naa ko dẹyin titi di inu oṣu kẹfa ọdun 2021 ti wọn tun kede wi pe Buhari ko si mọ, pẹlu alaye wi pe ẹni ti a n wo gẹgẹ bii Buhari kii ṣe Buhari, wi pe arakunrin kan ti wọn pe ni Jubril lati Sudan lo gbe aawọn rẹ wọ.
4. Bola Tinubu
Aarẹ orilẹede Naijiria lọwọlọwọ bayii, Bọla Ahmed Tinubu kii ṣe ajoji si awuyewuye ati awọn iroyin to nilo ọpọlọpọ iwadii ki a to le fi idi otito mulẹ.
Lara awọn iroyin ofege ti a ti gbọ nipa eekan oloṣelu naa tẹlẹri ni pe ibi ti o ti lọ gba itọju eto ilera nilu Oyinbo lo ti dakẹ.
Laarin oṣu kẹfa si ikejọ ọdun 2021 ni iroyin tun gba ode pe Tinubu ti ku, ṣugbọn irọ lasan ni.
Iroyin mii tun jade nipa ipapoda rẹ ninu oṣu kẹwaa ọdun 2022, ṣugbọn ko si ootọ nibẹ.
5. Rotimi Akeredolu
Gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolu ṣe aisan to lagbara lẹnu ọjọ mẹta yii, eyii lo si mu ki o lọ gba itọju loke okun.
Ọpọlọpọ iroyin la gbọ nipa ipapoda rẹ ninu oṣu kẹfa ọdun 2023 ki o to di pe oun gan an funra rẹ pada wa si Naijira ninu oṣu kẹsan an lẹyin oṣu mẹta nibi ti o ti lọ gba itọju.
6. Yakubu Gowon
A bi adara ologun orilẹede Naijiria tẹlẹri, Yakubu Gowon lọjọ kọkandinlogun oṣu kẹwaa ọdun 1934.
Ẹni ọdun mọkandinlaadọrun naa n foju wina iroyin ofege nipa iku aitọjọ lọwọlọwọ bayii.
Lọjọ kẹsan an oṣu kẹwaa ọdun yii ni iroyin kan n fo kiri ori ayelujara wi pe Gowon ti jade laye, ṣugbọn ki ilẹ ọjọ naa to ṣu lo ke sita wi pe ko si nnkan to ṣe oun o. Agbẹnusọ rẹ, Adeyeye Ajayi fi to awọn oniroyin leti wi pe alaafia ni ọga oun wa.