You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Ta ló rápálá wọ ìnú ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ Gómìnà ìpínlẹ̀ Osun, Ademola Adeleke tó fi ń dá họ́wùhọ́wù sílẹ̀?
Awọn onijibiti ori ayelujara kan ti gba akoso ọkan lara awọn ẹrọ ibanisọrọ gomina ipinlẹ Ọṣun, Ademọla Adeleke.
Agbẹnusọ fun gomina ipinlẹ Ọṣun, Ọlawale Rasheed lo sọ eyi ninu atẹjade kan to fi sita lọjọ Iṣẹgun.
Agbẹnusọ fun gomina Adeleke rọ araalu lati dẹyẹsi ipe kankan to ba kan siwọn lati ori nọmba ibanisọrọ +2348033657555.
Atẹjade naa ni wọn “ti n gbe igbesẹ to jọju lati yanju ọr naa”
O ni awọn ileeṣẹ alaabo ti n ṣe iwadii iṣẹlẹ naa ati lati daabo to yẹ bo awọn nọmba ibanisọrọ gomina naa.
- Adeleke, máṣe dáwọ́ ijó jíjó dúró àmọ́ mú ìṣèjọba rere ní pàtàkì l‘Osun - Obasanjo
- Ta ló tú ayédèrú dókítà tó gbẹ̀bí fún aláboyún tó kú sílẹ̀ lẹ́yìn táwọn agbófinró mú u nípínlẹ̀ Osun?
- Remi Tinubu ló ń bá mi wá ọ̀nà àbáyọ sọ́pọ̀ ìpèníjà tó ń kojú mi - Ademola Adeleke
- Kìí ṣe bàbá mi ló sọ mí ní Jackson, bí orúkọ náà ṣe wáyé nìyí - Gómìnà Adeleke
Tẹjade naa ko sọ ni pato ohun ti awọn onijibiti ori ayelujara naa ti da lara pẹlu nọmba gomina Adeleke amọṣa ohun ti wọn fi kọ atẹjade naa fihan pe ohun to ti da awọn to sun mọ gomina naa ati iṣejọba rẹ si hilahilo ni iṣẹlẹ naa.
Iṣẹlẹ gbigba akoso ẹrọ ibanisọrọ ẹni lọna aitọ kii ṣe tuntun lorilẹede Naijiria.
Ni ibẹrẹ ọdun 2024 ni iroyin jade pe awọn onijibiti ori ayelujara kan ti yọ wọ inu foonu sẹnetọ nigbakan ri, Tokunbọ Afikuyọmi to si padadu ẹgbẹlẹgbẹ owo nipasẹ rẹ.