Fayose: Ojuti nla ni aawọ nipa ibiti Leah Sharibu wa

Aworan Ayo Fayose

Oríṣun àwòrán, Facebook/Lere Olayinka

Àkọlé àwòrán, Ayo Fayose je alatako to foju han si ijọba orilẹẹde Naijiria
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Gomina ipinlẹ Ekiti, Ayodele Fayose ni, idojuti nla ni bi ileesẹ ọlọpa Naijiria ko ti se ni iroyin to peye nipa akẹkọ Dapchi kan to sẹku ti wọn ko tii ri.

O ni eyi se afihan aigboraẹniye to wa ninu ijọba to wa lode.

Loju opo Twitter rẹ loti lede ọrọ naa.

Skip X post
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post

O tesiwaju pe idojuti nla ni ki ọga ọlọpa wa si ori ẹro amohunmaworan apapọ lati tan ara ilu jẹ lori iroyin ti ko daa loju.

''Bi ọga ọlọpa ko ti se ni iroyin to peye lori Boko Haram, safihan bi darudapọ ti se gbode kan labe ijọba yi. Eyi mu ka gbosuba fun ọrọ ti minista fun eto aabo nigba kan ri, ajaagunfẹyinti Theophilus Danjuma so pe, ki awọn ọmọ orilẹẹde yi wa wọrọkọ fi sada lori pipese aabo fun ara wọn nitori pe ijọba to wa lode yi ko mo odo ti yoo da ọrunla si, nipa didabo bo ara ilu''

Amin iyasọtọ kan

Awọn iroyin ti ẹ lee nifẹẹ si:

Amin iyasọtọ kan

Lai pe yi ni ọga ọlọpa ni Naijiria, Ibrahim Idris, tako ọrọ ti awọn ileese iroyin kan gbe jade pe, oun sọ pe, ijọba yoo gbe akẹko Dapchi kan to ku pada wale laipe.