Kuburat Alaragbo Waka Queen: Tí èmi àti Salawa Abeni bá pàdé lórí "stage' lónìí, ẹrù ò ba odò tèmi o
"Baba mi ni Alhaji Ayinla Kolington jẹ́, ẹ̀gbọ́n mi ni onílù wọn tó máa ń jẹ́ ká gbaradì fún orin wa".
Alhaja Kuburat Alaragbo naa jẹ olorin Yoruba obinrin ti oun naa n kọ orin Waka yatọ si gbajugbaja ti awọn eeyan mọ iyẹn Queen Salawa Abeni.
gẹgẹ bi iwadi ati nkan ti oun funra rẹ sọ fun BBC Yoruba, Alaragbo gan ti n kọ orin lati ọjọ pipẹ bii ti Salawa Abeni ni ninu orin Waka bẹẹ si ni awọn to ba jẹ ololufẹ orin Waka gidi mọ ọ bi ẹni mọ owo tori oun naa di ilumọọka lasiko to n kọrin to si di olorukọ ṣugbọn o di asiko kan ti ko sẹni to rii mọ.
- A gbọ́dọ̀ padà sí ìlànà tà ń gbà jẹ Olubadan tẹ́lẹ̀ – Seyi Makinde
- De-General, àwọn mẹ́ta mìíràn wọ pańpẹ́ àjọ NDLEA torí egbògi olóró
- Wo àwọn ǹkan tó yẹ kí o mọ̀ nípa Alao Akala tó dágbére fáyé lẹ́ni ọdún 71
- Oluwo gbóríyìn fún Awujale, Akarigbo fún àyípadà òfin lórí àṣà àtijọ́ fún yíyàn Ọba, ṣíṣe ìsìnkú Ọba
- Pásítọ̀ David Ibiyeomie, adarí ìjọ Salvation Ministry tò dàwó sọ̀rọ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà
- Gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo tẹ́lẹ̀, Adebayo Alao-Akala ti jáde láyé
- Ọkọ mi pa ọmọ wa mẹ́ta, o kó òkú wọn sínú fírísà - Milliscent Amadikwa
- Ọ̀dọ́ márùn-ún forí la ikú nínú oko lọ́wọ́ agbébọn tó tún ṣèkọlù l'Ondo
Ẹwẹ, Kuburat Alaragbo ninu ifọrọwanilẹwo BBC Yoruba sọ pe digbi ṣi ni orin Waka n bẹ lẹnu koda o ni orin pọ sile amọ ọlaju atawọn nkan mii lo n ṣe idiwọ fun ai le gbe orin tuntun jade.
Ni nkan bii 1980s, Kuburat Alaragbo gbayii gidi gan pẹlu awọn orin rẹ.
Ọmọ bibi ilu Abeokuta ni Kuburat Alaragbo to ṣalaye idi ti wọn ko fi gburo rẹ mọ ati ohun to wa n ṣe bayii lati pada sori itage.

