You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Fashola ṣàlàyé ọ̀nà tuntun tí ìjọba àpapọ̀ Nàìjíríà gbé kalẹ̀ tí o fi lè di onílé
Ijọba apapọ orilẹede Naijiria yoo bẹrẹ tita awọn ile alakọra labẹ eto ikọle ọlọpọyanturu ti ijọba apapọ orilẹede Naijiria, National Mass Housing Programme.
Gẹgẹ bi minisita fọrọ iṣẹ ode ati ileegbe, Babatunde Raji Fashọla ṣe sọ, awọn ile naa yoo bẹrẹ lati ori miliọnu meje ati ẹgbẹrun lọna igba Naira (N7.2 million).
- Ẹgbẹ́ Afenifere kò gbàgbọ́ nínú yíyapa kúrò ní Naijiria - Ayo Adebanjo
- Ọwọ́ ikọ̀ Amotekun tẹ afurasí ajínigbé tó n múra bíi wèrè ní gáréèjì Akure
- Àjọ tó ń mójútó pínpín iná ọba fikún owó 'Metre' k'áráàlù lè sáré tete lọ gba 'Prepaid'
- Ọ̀pọ̀ arìnrìnàjò jóná, àwọn mìí tún farapa nínú ìjàmbá ọkọ̀ ní Okitipupa
Minisita Fashọla ṣalaye lasiko ti wọn n ṣi oju opo ayelujara fun eto ikọle naa nilu Abuja pe eyi yoo fun awọn ọmọ orilẹede Naijiria lanfani ati ra ile laisi iyanni ni pọsin tabi ṣegbe rara.
Bakan naa lo tun ṣalaye lori eto mohunmaworan abẹle kan pe iriri ti ko ṣee fi sẹnu rẹrin eyi tawọn ọmọ Naijiria ti doju kọ labẹ irufẹ eto yii tẹlẹ lo mu ki wọn gbe e lọ sori ayelujara.
O ni awọn ile yii wa kaakiri orilẹede Naijiria pẹlu afikun pe eyi ti owo ori rẹ pọ julọ ni miliọnu mẹrindinlogun ati ẹgbẹrun lọna aadọwa Naira. (N16.19 million).
Bakan naa ni Minisita Fashọla ṣalaye pe awọn ile bii ẹgbẹrun marun un ni wọn ti n kọ ti wọn si ti fẹrẹ pari kaakiri Naijiria.