You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
UN 76th session: Buhari ń bèèrè fún àforíjìn gbèsè Áfíríkà lọ́dọ̀ àjọ àgbáyé
Aarẹ orilẹede Naijiria, Muhammadu Buhari ba ijoko ajọ iṣọkan agbaye, UNP sọrọ lọjọ Ẹti niluu New York, lorilẹede Amẹrika.
Bo tilẹ jẹ pe akojọpọ ẹgbẹ ajijagbara to n beere fun iyapa kuro lara Naijiria, NINAS ṣe ifẹhonuhan niwaju olu ileeṣẹ UNO, ti ipade awọn olori orilẹede lagbaaye ti n waye, sibẹ aarẹ Buhari si pada sọrọ nibi ipade naa.
- Buhari san $500 fáwọn aláwọ̀ dúdú l‘Amẹ́ríkà láti takò ẹ̀hónú wa - Yoruba/Biafra Nation
- Agbẹjọ́rò Sunday Igboho fèsì padà fún Malami lórí ẹ̀sùn tuntun tó fẹ́ fi kan oníbàárà rẹ̀
- Èèmọ̀ wọ̀lú! Àrá sań pa bàbá, ìyá àti ọmọ wọn méjì
- Tá à bá ti ibodè tó wọ Naijiria, ìyà kò bá jẹ wá lásìkò Coronavirus - Buhari
- "Màálù tó ya sójú pópó kọlu ọ̀kadà ọkọ mí, tó sì kú ní ìkómọ ọmọ rẹ ku ọ̀la"
- Ọ̀pọ̀ àwọn tó fẹ́ ràn mí lọ́wọ́ ló fi ìlọ̀kulọ̀ lọ̀ mí, àyàfi Dudu Heritage nìkan
- 'Ó kéré tán, Nọ́ọ̀sí alábẹ́rẹ́ 7,000 ló ń sá kúrò ní Nàìjíríà ní ọdọọ́dún'
- Mílíọ́nù méje èèyàn ni ìdọ̀tì inú afẹ́fẹ́ "Air polution" ń pa lọ́dọodún - WHO
Oluranlọwọ aarẹ lori ọrọ iroyin, Femi Adesina lo ṣalaye ohun ti Buhari sọ nibi ipade naa ninu atẹjade kan to fi sita.
Wọnyii ni koko marun un ninu ọrọ ti Aarẹ Buhari sọ nibi ipade ajọ iṣọkan agbaye niluu New York.
Ẹ ba wa mojuto okoowo ohun ija oloro to di tọrọ fọn kale ni Afirika:
Aarẹ Buhari bu ẹnu atẹ lu owo nkan ija oloro lọna aitọ to ti wọpọ bayii nilẹ Afirika ati kaakiri agbaye.
Buhari sọ fun ijoko awọn olori orilẹede lagbaye eleyii to jẹ ẹlẹẹkẹrindinlọgọrin iru rẹ pe ọrọ naa n fẹ amojuto.
Aarẹ Naijiria ni tita ohun ija oloro yii lodi si ẹtọ ọmọniyan, ati pe ipa buruku ni eleyii n ni lawọn orilẹede Afirika.
Buhari sọ pe bi awọn eeyan kan ti n ṣe fayawọ nkan ija oloro lati orilẹede kan si omiran ko le bimọ 're fun orilẹede kankan.
Aarẹ Buhari tọrọ fun aforijin gbese Naijiria atawọn orilẹede ti ko rọwọ họri:
Aarẹ Buhari tun tọrọ aforijin gbese ti Naijiria atawọn orilẹede mii ti ko rọwọ họri jẹ papaa julọ bi ajakalẹ arun covid-19 ti ṣakoba fun ọrọ-aje awọn orilẹede naa.
Aarẹ Naijria ni ele ori gbese tawọn orilẹede ti ko tii goke agba n san tẹlẹ ṣaaju ajakalẹ arun coronavirus pọ ju.
O ni eyi ti ṣakoba fun ijọba lati le mojuto ọrọ ilera atawọn akanṣe iṣẹ idagbasoke mii fawọnb araalu.
Buhari ni iranwọ nla ni yoo jẹ fawọn orilẹede bayii ti awọn ajọ ayanilowo lagbaaye ba le fori gbese ti wọn jẹ jin wọn.
Buhari beere fun pinpin abẹrẹ ajẹsara covid-19 ni dọgba dọgba:
Aarẹ Buhari ko ṣai sọrọ lori pinpin abẹrẹ ajẹsara labẹ eto COVAX ti ajọ eleto ilera lagbaaye ṣe agbatẹru rẹ.
Buhari wa dupẹ lọwọ awọn to gbe eto yii kalẹ nitori Naijiria ti jẹ anfani lara eto naa.
Aarẹ Naijiria tun dupẹ lọwọ awọn orilẹede bi Amẹrika, Turkey, India, China, ajọ EU atawọn ajọ mii fun iranlọwọ ti wọn ṣe fun Naijiria lori dẹkun ajakalẹ arun coronavirus.
Amọ, aarẹ ni ọkan lara ọna lati le Covid-19 lọ pata pata ni pinpin abẹrẹ arun naa dọgba dọgba kaakiri orilẹede agbaaye.
Buhari bu atẹ lu iditẹgbajọba lapa iwọ oorun Afirika:
Aarẹ orilẹede Naijiria bu ẹnu atẹ lu iṣẹlẹ iditẹ gbajọba to waye lawọn orilẹede kan lapa iwọ oorun ilẹ Afirika bi Guinea ati Mali.
Buhari ni ifasẹyin ni eleyii jẹ pẹlu bi ijọba awarawa ṣe n fẹsẹ mulẹ lẹkun naa ati kaakiri ilẹ Afirika bayii.
O sọ nipa iranwọ ti Naijiria n ṣe pẹlu ajọ ECOWAS, AU ati UN lati wa ojutuu si ọrọ naa.
Buhari ni Naijria ti ran ikọ pẹtu sija lọ sawọn orilẹede ti iṣẹlẹ yii iditẹgbajọba yii ti waye lati pe fun imupada ijọba alagbada.
Buhari pe fun idokowo to mọyan lori pẹlu orilẹede agbaye:
Aarẹ Buhari idokowo to mọyan lori lai si ẹtan yoo ran ilẹ Afirika lọwọ.
Buhari ni ti awọn orilẹede Afirika ba le jẹ anfani okowo pẹlu awọn orilẹede to ti goke agba, wọn ko ni nilo iranwọ owo lati ọdọ wọn mọ.
Aarẹ ni anfaani si iru okowo bayii gan an nilẹ Afirika nilo ju owo iranwọ lati ọdọ awọn orilẹede to ti goke agba lọ.