You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Oyinkansola Elebuibon: Wọ́n ṣa mi ní àdá lọ́pọ̀ ìgbà, ṣùgbọ́n kò wọlé sí mi lára nítorí "Science?"
Oyinkansola Elebuibon, to jẹ ọkan lara awọn ọmọ Araba awo ilu Oṣogbo, Ifayemi Elebuibon, ti sọ pe oun iba ti jẹ Ọlọrun nipe bi kii ba ṣe ọpẹlọpẹ ajẹsara.
Oyinkansola lo fi ọrọ naa lede ninu ifọrọwerọ kan pẹlu BBC Yoruba.
Gẹgẹ bo ṣe ṣọ, awọn janduku kan ṣaa ni ada lọpọ igba, ṣugbọn ada naa ko wọle si lara.
Ṣaaju ni Oyinkansola ti kọkọ sọ ninu ifọrọwerọ naa pe ilẹ Amẹrika ni oun fi ṣebugbe bayii nitori awọn iṣẹlẹ to kan ṣẹlẹ si i nilu u Ibadan lọdun 2019.
Iṣẹlẹ naa jẹ eyii to gbomi loju Oyinkansọla, koda, bintin bayii lo ku ki omi bọ loju rẹ lasikọ to n ṣalaye ọrọ naa fun BBC Yoruba.
Oyinkansola ni "Alẹ ọjọ kan lẹyin ti mo ti ode ere de ni awọn kan wa da emi atawọn ọmọ to n gbe pẹlu mi mọle, wọn gba owo ati awọn nnkan miran lọwọ wa."
"Ṣugbọn nigba to ya, wọn ni ki n wọle sinu yara, mo si ṣe bẹẹ, lẹyin ti wọn ko awọn ẹgba ọrun tan ni wọn ba ni ki n dubulẹ sori ibusun ti mo si kọ."
- Ilé ẹjọ́ tú ìgbéyàwó ọlọ́mọ mẹ́jọ ká nítorí pé ọkọ rí àwọn òbí ìyàwó fín
- Gbèǹdéke ẹ̀mí gígùn àwọn ọmọ Naijiria kò ju ọdún 54 lọ - Ẹgbẹ́ àwọn dókítà
- Ta ni Ousmane Sonko, tí wàhálà bẹ́ sílẹ̀ ní Senegal lẹ́yìn tí ìjọba fòfin mú u?
- Ó ṣòro púpọ̀ láti mọ ayédèrú òṣìṣẹ́ LASTMA ní ìpínlẹ̀ Eko, ṣùgbọ́n..-Agbenusọ àjọ LASTMA
- Àwọn òsìṣẹ́ ètò ìlera ti bẹ̀rẹ̀ sí ń gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19 ní Naijiria, wo ìgbà tí yóò kàn ọ́
Ninu alaye rẹ, o sọ siwaju si pe "Lẹyin ti mo bọ lọwọ wọn tan ninu ile ni mo ba ni ki n jade lẹnu ilẹkun nla to wọ inu ile ni mo to ranti pe mo ti ti ilẹkun naa pa."
"Bi awọn eeyan yii ṣe jade simi niyẹn ti wọn si bẹrẹ si n ṣa mi ladaa, ṣugbọn ko wọle, o kan fi apa diẹ simi lara ni."
- Nǹkan dé, Igboho ní káwọn ọ̀dọ́ ilẹ̀ Yorùbá lọ múra ògùn jọ nítorí ohun tó ń bọ̀ lọ́nà
- Ọlọrun má jẹ́ kí a jẹ́ gbèsè lókù báyìí tí a kò kó ọjá lọ sílẹ̀ Yorùbá mọ́- Hausa Oníṣòwò
- Àwọn tó jí akẹ́kọ̀ọ́bìnrin gbé ní Zamfara fẹ́ yẹ̀yẹ́ Ìjọba Buhari ni- Hadi Sirika
- Ohun tó yẹ kí ó mọ̀ nípa oríṣìíríṣìí ìlẹ̀kẹ̀ ìbàdí rè é
O ṣalaye pe "ọpẹlọpẹ 'science' ni ko jẹ ki ada naa wọle simi lara, n o ba ti gba ibẹ lọ."
Ṣugbọn nigba ti atọkun BBC Yoruba bere pe ki lo n jẹ "science" ti Oyinkansola n sọ, lo ṣi aṣọ loju eegun pe oogun abẹnu gọngọ ni oun n poe ni 'science.'
Yatọ si eyii, Oyinkansola tun sọrọ nipa bi ere ori itage ṣe jẹ ajogun ba fun oun, ati bi ko ṣe ti oun loju lati jẹ onigabgbọ ninu ẹsin adayeba ilẹ Yoruba, paapaa Ifa Olokun asọrọ dayọ.
Oyinkansola sọ pe lara afojusun oun fun ọjọ iwaju ni pe yoo wu oun lati gbe aṣa Yoruna ga ju bo ṣe wa lasiko yii lọ.
Nipa ibasẹpọ to wa laarin oun ati oṣere tiata kan ti irawọ rẹ n tan lọwọ yii, ti awọn kan sọ pe awọn mejeji ni ibasẹpọ, ati pe gbajumọ oṣere naa lo gbe lọ silẹ Amẹrika, Oyinkansola sọ pe ko si ohun to jọ bẹẹ rara.
- Ọ̀jọ̀gbọ́n Ijeoma ní òun kìí ṣe ọmọ Nàìjíríà mọ́, South Africa tó yàn dípò bá tún lé e jáde
- 'Tinubu kò ṣe nǹkan ètùfù tó lè fi máa kíyèsí ẹ̀yìnkùlé nítorí EFCC'
- Àwọn ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ tó dá mi lọ́nà lọ́jọ́ Ẹtì fẹ́ pa mí ni -Sunday Igboho
- Àwọn òṣìṣẹ́ Shoprite bẹ̀rẹ̀ ìfẹ̀hónúhàn ní Ibadan, Akure, Eko àtàwọn ìlú míràn