You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Oyo physically challenged protest: Ìdí rèé táwọn àkàndá ẹ̀dá fi dí iwájú iléeṣẹ́ ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo pa l'Agodi n'Ibadan
Sunkẹrẹ fakẹrẹ gbode kan l'Agodi niluu Ibadan lọjọ Aje ọjọ keje oṣu kejila ọdun 2020 yii lẹyin tawọn onipenija ara bọ soju popo lati fẹhonuhan.
Awọn akanda ẹda ọhun to wa lati ijọba ibilẹ mẹtalelọgbọn kaakiri ipinlẹ Oyo lu oju opo ileeṣẹ ijọba to wa lagbegbe Agodi n'Ibadan pa.
Ohun ti wọn n beere ni pe ki ijọba gba awọn onipenija ara sii ninu awọn oṣiṣẹ ti kii ṣe awọn olukọ lawọn ileewe kaakiri ipinlẹ Oyo.
- Kò sí ẹnikẹ́ni tó kú níbi rògbòdìyàn tó wáyé lánàá - Deji ilu Akure
- Ọlọ́pàá, sójà yabo Lekki Toll Plaza láti dènà ìfẹ̀hónúhàn míràn
- Gbọ́yì-sọ̀yí àti ìròyìn èké láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ wa ló ṣáábà ma ń da ìgbéyàwó àwọn òṣèré rú- Ọpẹ Ayeola
- Idi ti Odili fi gba ibi ìbálòpọ̀ lọ sí ọ̀run alákeji nílùú Port Harcourt
- Makinde, Dele Momodu ń ṣèdárò Àgbà Oyè Ilẹ̀ Ibadan, Harry Akande tó jáde láyé
Laipẹ yii ni Gomina Seyi Makinde sọ pe ki ajọ to n ri si ọrọ awọn olukọ gba ẹgbẹrun un meje olukọ, ati ẹgbẹrun un meji awọn ti kii ṣe olukọ nipinlẹ Oyo.
Gomina Makinde tun sọ pe ki wọn gba awọn oṣiṣẹ eleto abo megaadi ẹgbẹjọ.
Amọ awọn akanda eeyan to n ṣe iwọde ṣalaye pe awọn ti ijọba mu ninu awọn ti kere ju.
Wọn ni awọn n rawọ ẹbẹ si Gomina Makinde lati wa nkan ṣe si ọrọ naa.
Awọn olufẹhonuhan naa duro wamu wamu sẹnu geeti to wọ ileeṣẹ ijọba ipinlẹ Oyo eleyi ti ko jẹ kawọn oṣiṣẹ ri aye wọle.
Awọn to ni ipenija ara sọ pe awọn lo sun mọ oṣi ati iṣẹ ju awọn abarapa eeyan lọ.
Ọkan lara awọn akanda ẹda naa to bawọn akọroyin sọrọ, Adegbuyi Adekunle ṣalaye pe ida marun un ninu ọgọrun tii ṣe 350 lo yẹ ki wọn fawọn.
O ni eeyan mọkandinlaadọjọ(149) pere ni ijọba fun ni iṣẹ ninu awọn ti wọn ṣẹṣẹ gba.
- Ṣé ẹ rántí àkọ́lé àwọn ìwé àkàgbádùn yìí?
- Àwọn Olúkọ ìpínlẹ̀ Oyo fakọyọ lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà púpọ̀
- Rògbòdìyàn bẹ́ sílẹ̀ láàrin àwọn ọlọ́kadà àti àwọn òṣìṣẹ́ ọgbà ẹ̀wọ̀n ní Ibadan
- Wo àwọn oúnjẹ márùn ún tó ń mú kí àtọ̀ ọkùnrin dára síi
- Ọdun 2012, 2016 àti 2020 ni John Mahama àti Nana Akufo-Addo ti jọ ń figagbága dupò aàrẹ Ghana