You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Tola Ogundipe: Òṣìṣẹ́ mẹ́rin bọ́ sí gbaga ọlọ́pàá lórí ikú ọ̀gá wọn tó rì sómi
Igbakeji Ọga Agba ileeṣẹ to n risi ọrọ owo ori, Price Water Coopers , PwC Nigeria , Tola Ogundipẹ ti jade laye.
Ọjọ Satide ni wọn ti bẹrẹ si ni wa arakunrin naa lẹyin to wọ ọkọ oju omi ni ipinlẹ Eko.
Ọjọ Aiku ni wọn ri ọkọ oju omi naa amọ ti awọn ọlọpaa to n ṣiṣẹ lori omi si ri oku rẹ ni Ọjọ Aje.
Agbẹnusọ fun ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Eko, Muyiwa Adejọbi sọ wi pe, lootọ ni iṣẹlẹ naa waye, awọn oṣiṣẹ oloogbe mẹrin ni awọn ti fi ọrọ wa lẹnu wo.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- A gbé òfin 1960 jáde, màálù tó bá jẹ oko àgbẹ̀, tí olówo rẹ̀ kò sanwó, títà ni - Buhari
- Ìjọba fẹ́ kọ́lé 300,000, pẹ̀lú ìrànwọ́ fún àgbẹ̀ 4m láti mú àdínkù bá ìṣẹ́ - Osinbajo
- Wò ó bí Alaafin àti aya àkọ́fẹ́ rẹ̀, Olorì Abibat ṣe pàdé ní èwe
- Coronavirus ti fa ọ̀wọ́ngógó oúnjẹ ní ìpínlẹ̀ Eko, Kano, Rivers àti Abuja- NBS
- Àwọn èrò yarí lórí sísan owó àyẹwò covid-19 bí bàálù ilẹ̀ òkèèrè ti ba s'Abuja lẹyìn oṣù márùn ún
- Ẹ wo ààrẹ orílẹ̀-èdè tó ń ṣèdárò Ẹja akóredé tó d'olóògbé
- Àbá àpérò 2014 CONFAB lojútùú sí àtúnṣe ìwé òfin Nàìjíríà- Afenifere sáwọn sẹ́nẹ́tọ̀
O salaye wi pe, Kọmisọna ọlọpaa nipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu ti paṣẹ iwadii idakọnkọ lori iṣẹlẹ naa.
'' A ti gbe iṣẹlẹ naa lọ si ẹka to n risi ọrọ iwa ọdaran ni Yaba, nipinlẹ Eko lati ṣe iwadii naa lẹkunrẹrẹ.''
''Ti iwadii ba pari, ileeṣẹ ọlọpaa yoo fi abajade han si gbangba.''
Ninu ọrọ ti ileeṣẹ Price Waterhouse Coopers fi lede, Ọga agba patapata ni Naijiria, Uyi Akpata sapejuwe Ogundipẹ to doloogbe naa, gẹgẹ bi ẹni to n ṣe iṣẹ rẹ doju ami.
Ko to di oloogbe, Tola Ogundipe ṣiṣẹ gẹgẹ bi adari ẹka PwC Africa Tax , Assurance Leader for PwC Africa ati awọn ipo miran to dimu ninu ilẹeṣẹ PwC.
Ileeṣẹ Price Waterhouse Coopers ni awọn yoo fi ọjọ isinku rẹ lede lẹyin ijiroro pẹlu awọn ẹbi ati ara oloogbe naa.