You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
MKO Abiola: Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ àwọn olè tó kó góòlù àti ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ mílíọ̀nù lọ nílé Abiola l'Eko
Ileeṣẹ ọlọpaa ti mu awọn afurasi adigunjale to ṣọṣẹ nile oloogbe Oloye Moshood Abiola to wa ni Ikeja niluu Eko nibi ti wọn ti ji nkan to to ẹgbẹlẹgbẹ miliọnu lọ.
Abiola lo jawe olubori ninu ibo aarẹ gbogbogbo to waye lọdun 1993 eyi ọgagun fẹyinti Ibrahim Babangida wọgile nigba naa.
Kọmiṣọnna ọlọpaa nipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu lo sọ pe ọwọ awọn agbofinro ti tẹ awọn kọlọnbiti ẹda ọhun ti wọn yabo ile Abiola l'Ọjọru.
- Ààrẹ Buhari pọ́n ọ̀dọ́ Nàíjíríà lé, ó ya Nov 1st sọ́tọ̀ fún àyájọ́ ọ̀dọ́
- Àwọn ọba Yorùbá kan rèé tí wọ́n rọ̀ lóyè, tí ọba míràn jẹ lójú ayé wọn
- Duro Ladipọ, ìlúmọ̀ọ́ká òṣèré tíátà àti ọmọ àlúfà tí kò gbàgbé àṣà ìbílẹ̀
- Ìtàn Àrọ̀gìdìgbà jẹ́ kí ń rò pé bàbá mi yan Yemọ̀ja ní àlè - Ọmọ Fagunwa
- MKO Abiola, iṣẹ́ aṣẹ́gità ló fi bẹ̀rẹ̀ okoòwò
- Ọba Saudi Arabia yọ ọmọ rẹ̀ àti àbúrò rẹ̀ kúrò nípò nítorí ìwà àjẹbánu lórí owó tó yẹ fún ààbò ìlú
Kọmiṣọnna ọlọpaa to ṣabẹwo si ile ọhun fidi rẹ mulẹ pe mẹta lawọn ole ọhun ṣugbọn ọkan lara wọn lo gbe ibọn dani.
Ọgbẹni Odumosu ni ''ẹbi Abiola sọ f'oun pe awọn ole naa ji ọpọlọpọ goolu ati owo lọ.''
''Awọn agbofinro ti wa lojufo bayii legbegbe Ikeja ti ile naa wa to fi de ọdọ awọn ọlọpaa to wa ni ibode Idiroko ati Seme,'' kọmiṣọnna ọlọpaa lo sọ bẹẹ.
Kọmiṣọnna ọlọpaa ipinlẹ Eko ni ko si ẹni to farapa ninu iṣẹlẹ naa ninu iyawo Abiola, Bisi ati ọmọbinrin meji to wa nile.
Ọgbẹni Odumosu fikun ọrọ rẹ pe iwadii ṣi n lọ siwaju lori iṣẹlẹ naa.
Awọn aladugbo to bawọn akọroyin sọrọ ṣalaye pe geeti to wa lẹyin lawọn ole ba wọle, wọn ni laago mẹrin idaji ni iṣẹlẹ naa waye nigba tawọn ẹṣọ to wa nile ile naa ti sun lọ.
- Bàbá ẹni ọgọ́ta ọdún dèrò ilé ẹjọ́ nítorí ó wọ inú oko Obasanjo láì gba àṣẹ
- Bí ìjà bá wà láàrin èmi àti Olubadan, a ó yanjú ẹ ní pẹ̀lẹ́kùtù, ọ̀rọ̀ bàbálọ́jà kò lè dìjà
- Wo ọ̀nà tí o le è gbà láti má san àfikún owó iná ẹ̀lẹ́ńtíríìkì tuntun
- Mi ò fẹ́ ìrànwọ́ ẹgbẹ́ òṣèré, àwọn kọ́ ló kóbá mi- Chief Kanran
- E wo ọmọ Yorùbá àkọ́kọ́ tó jà fún ẹ̀tọ́ àwọn aláwọ̀dúdú ní America!