Buhari mú ayé dẹrun fún àwọn ọmọ Nàìjíríà ju àwọn ìjọba àtẹ̀yìnwá lọ- Lai Mohammed

Minisita eto ibanisọrọ ati iroyin, Lai Mohammed ti gboriyin fun ijọba aarẹ Muhammadu Buhari lẹyin to ni ijọba ọhun pese awọn ohun amayedẹrun fun awọn ọmọ Naijiria.

Bo tilẹ jẹ pe awọn ọmọ Naijiria kan koro oju si ina ijọba ti ko ṣe dede ati ọna to ti mẹhẹ, ọgbẹni Lai sọ pe ijọba Buhari pegede bo ṣe pese awọn ohun amayedẹrun.

O ni ijọba Buhari pegede ju gbogbo ijọba to ti ṣaaju lọ ni pipese awọn ohun amayedẹrun fun awọn Naijiria.

Agbẹnusọ ijọba lo sọ ọrọ yii nibi ifọrọwerọ pẹlu awọn oniroyin, nibi to ti n ṣe alakalẹ aṣeyọri ijọba Buhari lọdun 2019.

Lai sọ pe "Bi a ṣe n sọrọ yii, awọn ohun amayedẹrun bii opopona, ọna oju irin, ina mọnamọna, ati awọn ouhn miran ni ijọba yii n ṣe lọwọ."

O tẹsiwaju pe "Ko tii si ijọba kankan to gunle iru iṣe bayii, papa julọ ni igabti ọrọ aje dẹnu kọlẹ."

Ọgbẹni Lai ni ko si ijọba kankan ti yoo la oju rẹ silẹ ki ilu bajẹ mọọ lori.

O ni owo ti ijọba apapọ n ya jẹ lati fi pese awọn amayedẹrun mii ti yoo mu ki ọrọ aje orilẹ-ede Naijiria gberu sii.