Iku Fẹ́lẹ́: MC Oluọmọ, àwọn èèkàn ìlú sọ̀rọ̀ lórí ikú alága NURTW, Fẹ́lẹ́

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 4

Ọpọ awọn eekan ẹgbẹ awakọ ero lorilẹede Naijiria ni wọn peju sibi isinku oloogbe Taofeek Oyerinde ti pupọ eeyan mọ si Fẹlẹ.

Isinku rẹ waye nilu Ibadan ni ibamu pẹlu ilana ẹsin musulumi.

Lara awọn eekan to peju sibẹ naa ni MC Oluọmọ, ẹni to jẹ ilumọọka aṣiwaju ẹgbẹ ọlọkọ ero NURTW nipinlẹ Eko.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

MC Oluọmọ ni obitibiti ero to peju kii ṣe iyalẹnu nitori irufẹ eeyan ti oloogbe Fẹlẹ jẹ nigba aye rẹ.

Lara awọn miran to peju sibẹ ni aṣoju ijọba ipinlẹ Ọyọ, Kọmiṣọna ọlọpaa nipinlẹ Ọyọ, awọn agba ẹgbẹ awakọ ero nipinlẹ ati ni apapọ orilẹede Naijiria.

Ikú Fẹ́lẹ́: Àwọn olùbánikẹ́dùn ní Fẹ́lẹ́ kò dúró jẹ isẹ́ ọwọ́ rẹ̀.

Obitibiti ero kora jọpọ lati kẹdun nile alaga NURTW ẹkun gúúsù -ìwọ̀-oorunTọtun tosi ni igbe ẹkun ati idaro ti n sọ lasiko ti ẹbi, ara, ọrẹ, ojulumọ ati awọn alabaṣiṣẹ pọ kora jọpọ, lati kẹdun nile alaga ẹgbẹ awọn awakọ NURTW ipinlẹ Ọyọ, Alhaji Taofeek Oyerinde Fẹlẹ, to padanu ẹmi rẹ sọwọ aisan kidinrin lọjọ isẹgun.

Fẹlẹ́, tó jẹ alága ẹgbẹ́ ọlọ́kọ̀ èrò ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, dagbere faye lẹ́ni ọdún méjìdínlọ́gọ́ta

Awọn oloselu, asoju ẹgbẹ awakọ jakejado ẹkun iwọ orun-guusu, to fimọ awọn amuludun naa ko gbẹyin nile oloogbe.Lara awọn eeyan to ba ikọ BBC Yoruba sọrọ nile oloogbe ni agbegbe ẹlẹbu nilu Ibadan, ṣe apejuwe ipapoda Alhaji Fẹlẹ gẹgẹ bii adanu nla fun ẹgbẹ NURTW ati ipinlẹ Ọyọ lapapọ.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Wọn fi kun ọrọ wọn wipe, oloogbe naa to dagbere faye lẹni ọdun mejidinlọgọta ni ko duro jẹ ere ise rẹ, gẹgẹ bi wọn se rawọ ẹbẹ si Ọlọrun lati tu aya, ọmọ ati awọn mọlẹbi to fi silẹ ninu.Alhaji Taofeek Oyerinde Fẹ́lẹ́, ti o jẹ alaga ẹgbẹ awọn awako NURTW ipinlẹ Ọyọ jade laye lọjọ isegun, nile iwosan to n risi itọju kindinrin nilu Abuja nipasẹ aisan kindinrin to baa finra.

Ìṣẹ́ kọ̀ndọ́ ní Fẹ́lẹ́ fí bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ níbẹ̀rẹ̀ ayé rẹ̀

Alága àwọn awakọ̀ ní ìhà gúúsù-ìwọ̀-oòrùn (NURTW) Alhaji Taofeek Oyerinde tí gbogbo ènìyàn mọ̀ sí Fẹ́lẹ́ tún jẹ́ alága ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́.

Ó kú ní ọ̀san àná ọjọ́ kẹ́jọ oṣù kẹjọ, ọdún 2018, ní ilé ìwòsàn Zenith Medical Kidney Hospital Abuja lẹ́yìn àìsàn kídìrín.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Wọn ó sin ni Elebu, Ibadan láàrọ òní nílànà ẹ̀sìn Musulumi, Oyerinde dí alága ẹgbẹ́ awakọ ní 2011, ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ kọ̀ndọ́ bọ́ọ̀sì ní ọdún 1975, ó gba ìwé ọkọ ìrìnà ní 1979 nígbà to dí ọmọ ẹgbk tó fẹsẹ̀ rinlẹ̀ láti 'ọdun 1983 titi tó fi kú.

Lẹ́yìn ìkú rẹ̀ ní Gómìnà Ọyọ́ Abiola Isiaka Ajimobi tí gbà pẹ̀lú olórí NURTW tí àpàpọ̀ láti fi Abideen Olajide tí gbogbo ènìyàn mọ sí Ejìogbè bọ́ sípò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí adelé alága.

Lójó òpó twitter àwọn ọmọ Nàìjírtíà ń ṣelédè lẹ́yìn rẹ̀.

Àìsàn kíndìnrín tó dasẹ́ sílẹ̀ ló pa Fẹ́lẹ́ - Ààrẹ NURTW

Loni, Ọjọru ni wọn yoo fi iyoku ara alaga ẹgbẹ ọlọkọ ero (NURTW) nipinlẹ Ọyọ, Alhaji Taofeek Oyerinde, ti gbogbo eeyan mọ si Fẹlẹ, fun ilẹ.

Atẹjade kan ti aarẹ ẹgbẹ Nurtw nilẹ wa, Alhaji Najim Yasin fisita ni aisan to nii se pẹlu kindinrin Fẹlẹ to da isẹ silẹ, lo se okunfa iku rẹ.

A gbọ pe aisan naa ti n se Fẹlẹ, to tun jẹ alaga ẹgbẹ ọlọkọ ero lẹkun iwọ oorun ilẹ yii, lati bii ọjọ melo kan, ti wọn si ni ni ode lọsẹ mẹfa sẹyin lasiko ipade igbimọ alasẹ ẹgbẹ naa nipinlẹ Ọyọ, eyi to waye ni olu ileesẹ Nurtw tuntun ni adugbo Ọjọọ, nilu Ibadan.

Atẹjade naa ni ile Fẹlẹ to wa ni adugbo Ẹlẹbu nilu Ibadan ni wọn yoo sin oloogbe naa si ni aago mẹsan si mẹwa oorọ yii.

Najim Yasin, ẹni to ni orilẹ-ede Saudi Arabia ni oun wa fun haji, wa se apejuwe oloogbe Oyerinde Fẹlẹ bii ololufẹ alaafia, to si gbadura pe ki Ọlọrun gba abọ rẹ.

Iku Fẹlẹ ti wọn kede lojiji yii lo mu ki ayẹyẹ ọdun ileya tete di wẹlo ninu ile rẹ, ti awọn ẹbi rẹ si bẹrẹ si se ọfọ rẹ.

Bakan naa ni wọn tete palẹ awọn tẹnti ati aga ọdun mọ nilẹ.

Ikede iku Fẹlẹ

Ni ọsan ọjọ Iṣẹgun ni Alhaji Fẹlẹ jade laye nileewosan Zenith Kidney Hospital nilu Abuja.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ninu ọrọ to ba BBC Yoruba sọ lati orilẹede Saudi Arabia, Aarẹ ẹgbẹ awakọ ero l'orilẹede Naijiria, Alhaji Najeem Yasin ni ''dokita to n tọju oloogbe Taofeek Oyerinde lo pe oun lati tufọ rẹ ati pe ohun ti ṣe eto bi oku oloogbe naa yoo ṣe de ilu Ibadan lati ilu Abuja ni.

Alhaji Fẹlẹ, gẹgẹbi aarẹ ẹgbẹ NURTW lorilẹede Naijiria ṣe sọ, ti wa ni ile iwosan lati nnkan bii ọsẹ mẹta sẹyin, nibi ti o ti n gba iwosan fun aisan kidinrin to ba n finra.

"Ọsẹ mẹta lo ti wa ni ileewosan Zenith Kidney hospital nibi ti o ti n gba itọju.

Aisan kidinrin lo n yọọ lẹnu, aisan naa lo si ṣokunfa iku rẹ lọsan oni."

Ki oto dagbere faye, Alhaji Oyerinde Fẹlẹ ni alaga ẹgbẹ awakọero NURTW lẹkun iwọ oorun gusu orilẹede Naijiria.