Ekiti Election: Èyí ni àwọn olóṣèlú Nàìjíríà tó tí 'fọ́gbọ́n ṣàìsàn'

Oríṣun àwòrán, @ogundamisi
Oríṣiríṣi awuyewuye ló tí jẹyọ lórí ìṣẹ́lẹ́ tó wáyé ní ìpínlẹ̀ Ekiti l'Ọ́jọ́rú, níbití Gómìnà Ayọdele Fayose ti 'kán l'ọ́rún' nípasẹ̀ afẹ́fẹ́ tajú-tajú.
Fayose fi ẹ̀sùn kan ìjọba àpapọ̀ Nàìjíríà pé ó rán àwọn ọlọ́pàá sí ìpínlẹ̀ Ekiti láti pá òun ṣáàjú ètò ìdìbò gómìnà tí yóò wáyé lọ́jọ́ kẹrìnlá, òṣù Keje.
Kín ni àwọn ọmọ Nàìjíríà n sọ lórí ọ̀rọ̀ Fayoṣe?
Èrò àwọn aráàlú kò jọ ara wọn lórí ọ̀rọ̀ Fayosẹ. Bí àwọn kan sẹ gbàgbọ́ pé ọgbọ́n arékérekè ni Fayose n dá, ni àwọn kan ni ìfìyà jẹ ni ìṣẹ̀lẹ̀ nàá.

Joseph Ọlanrewaju sọ lórí Facebook pé ''nkan ti wọ́n ṣe fún Fayose ati ẹgbẹ́ òṣèlú rẹ̀ kò dára rárá.''

Ṣùgbọ́n Fayose kọ́ ni olóṣèlú Nàìjíríà àkọ́kọ́ tí àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà fẹ́sùn kàn pé ó parọ́ pé ìlera àwọn kò pé, yálà nítorí pé wọ́n ní ẹjọ́ láti jẹ́ tàbí nínú wàhálà òṣèlú.
Dino Melaye nàá tí kán l'ọ́rùn rí
Láìpẹ́ yìí ni iléèṣẹ́ ọlọ́pàá Nàìjíríà gbé aṣòfin Dino Melaye lọ sílé ẹjọ́.
Bi ó tilẹ̀ jẹ́ pé orí ibùsùn aláìsàn ló wà lásìkò nàá, èyí kò dáwọn dúró láti gbé aṣòfin nàá, tí wọn fẹ̀sùn ìwà ọ̀daràn kàn lọ síwájú ilé ẹjọ́.

Oríṣun àwòrán, @dinomelaye
Ṣùgbọ́n Melaye kọ́ ni olóṣèlú Nàìjíríà tí yóò kọ́kọ́ lọ sílé ẹjọ́ lórí àketè àìsàn.
Olisah Metuh nàá ṣe bẹ̀ ẹ́
Olisah Metuh, tó ti fìgbàkan jẹ́ akọ̀wé ìpolongo gbogboogbò fún ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party, PDP, farahàn nílé ẹjọ́ gíga tìjọba apapọ̀ nílùú Abuja, lọ́jọ́ karùn ún, oṣù Kejì, 2018 lórí kẹ̀kẹ́ aláàrẹ̀, lásìkò tó lọ fún ìgbẹ́jọ́ ẹ̀sùn gbígba irinwó mílíọ́nù Naira láti ọ́ọ̀físì olùgbani nímọ́ràn lóri ètò àábò gbogboogbò lọ́dún 2014, ṣáàjú ètò ìdìbò gbogboogbò tó wáyé lọ́dún 2015.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Èyí mú kí onídàjọ́ Okon Abang, sún ìgbẹ́jọ́ rẹ̀ sí ọjọ́ mì í.
Femi Fani-Kayode nàá kò gbẹ́yìn
Ẹlòmìí tó tún ti ṣe bẹ̀ ẹ́ ni mínísítà fún ìgbòkè-gbodò ìrìnnà ojú òfurufú, Femi Fani-Kayọde, lásìkò tí agbẹjọ́rò rẹ̀, Norrison Quakers, sọ nílé ẹjọ́ lọ̀jọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n, oṣù Kínní, 2018, pé oníbàárà òun kò lè wá fún ìgbẹ́jọ́ nítorí àìsàn tó ní i ṣe pẹ̀lú ọkàn.
Norrison ní "ìyàwó oníbàárà òun ló pe òun lórí ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ pé ìléèwòsàn ti gba ọkọ òun nítẹ̀ẹ́.
Ṣàájú ni wọ́n ti fi ẹ̀sùn lílu owó tó n lọ sí bi i mílíọ́nù máàrùn Naira, tó jẹ́ owó ìlú ní pónpó kàn án àti àwọn méjì mì í.
Nenadi Usman nàá darapọ̀ mọ́ wọn
Mínísítà fún ètò ìnáwó nígbàkan rí, Abílékọ Nenadi Usman, tí wọ́n jọ fi ẹ̀sùn kan òun àti Fẹmi Fani-Kayọde, lọ̀jọ́ karùn ún, oṣù Kejìlá, 2017 nàá bẹ ilé ẹjọ́ gíga tìjọba àpapọ̀ tó wà ní ìlú Èkó láti fún un láàyè kó lọ sí ilẹ̀ Amẹrika fún ètò ìlera rẹ̀.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Sáàjú ló ti sọ fún ilé ẹjọ́ pé àìsàn jẹjẹrẹ n bá òun fínra. Ile ẹjọ́ gba ẹ̀bẹ̀ rẹ̀.
Ẹ̀sùn mẹ́tàdìnlógún ni àjọ EFCC fi kàn án, àti Fani-Kayọde, tó fi mọ́ alága nígbàkan rí fún ẹgbẹ́ àwọn ìjọba ìbẹ́lẹ̀ ní Nàìjíríà, Ọ̀gbẹ́ni Yusuf Danjuma.
















