Fani-Kayode: Iwà Dino dójútini gẹ́gẹ́ bí olóṣèlú

Oríṣun àwòrán, Twitter
Mínísítà nígbà kan rí, Femi Fani-Kayode, ti bẹnu àtẹ́ lu ìwà Sẹ́nétọ̀ Dino Melaye, nígbà tí àwọn ọlọ́pàá ń gbée látì Abuja lọ sí Kogi tí ó sì fẹsẹ̀ fẹ.
Ẹ ó rantí wí pé ní ọjọ́ ìṣẹgun ni ìròyìn gbálẹ̀ pé Dino ti jọ̀wọ́ ará rẹ̀ fún àwọn ọlọ́paa. Kò pé sí ìgbà náà ni àwọn fídíò bẹrẹ sí ní gba orí ẹ̀rọ ayélujára, to ṣe àfihàn Dino níbi tí o joko sí ilẹ̀ láàrin ojú títì ní Ábuja.
Fani-Kayode sọ lórí Twitter ní Ojoru wí pé bí Melaye ṣe hùwà nínú fídíò ìṣẹ̀lẹ̀ náà kò fi akin àti iyì hàn.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Ó ní, kò yẹ ènìyàn tó jẹ́ Sẹ́nétọ̀ hùwà bẹ́ẹ̀, bí ó ti lẹ̀ jẹ́ pé òun kórira bí Aare Muhammadu Buhari ṣe ń ṣe sí àwọn tí ó gbe sórí oyè.








