Ọmọ ọdún 15 fojú balé ẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé ó bá ọmọ ọdún mẹ́jọ lòpọ̀

Oríṣun àwòrán, thesetimesmedia
Ọmọ ọdun marundinlogun kan ti kawọ pọn rojọ niwaju adajọ Majistreeti kan niluu Eko lori ẹsun pe o fọwọ kan ọmọ ọdun mẹjọ lọna ti ko tọ.
Ileeṣe ọlọpaa gbe ọmọ naa lọ sile ẹjọ lori ẹsun ibalopọ lọna aitọ.
Ọlọpaa to n ṣe ẹjọ ọhun, ASP Akpan Nko ṣalaye fun ile ẹjọ naa pe afurasi wu iwa ọdanran naa lọjọ kẹsan an, oṣu Keji, ọdun 2022 ni adugbo Oladejo, ni Araromi, Badagry, nipinlẹ Eko.
- Ilé ẹjọ́ fi Rahman Adedoyin pamọ́ sí ọgbà ẹ̀wọ̀n bí ìgbẹ́jọ́ ikú Timothy Adegoke ṣe bẹ̀rẹ̀ l'Osun
- Ìjọba àpapọ̀ fún Amẹ́ríkà láṣẹ láti gbé Abba Kyari fún ìgbẹ́jọ́
- Kíni ó wà nínú lẹ́tà tí ọkùnrin tí wọ́n bá òkú rẹ̀ pẹ̀lú obìnrin kan nínú mọ́tò kọ sí aya rẹ̀?
- Ìdí tí mi ò fi kópa níbi ìpàdé ìpẹ̀tùsááwọ̀ láàárín èmi àti Aregbesola nìyìí – Tinubu
- MC Oluomo, ilá rẹ fẹ́ máa ga ju onírè lọ - NURTW
- Àwọn ọmọ Nàìjíríà tó wà ní Ukraine yóò máa dé láti òní lọ- Mínísítà fọ́rọ̀ ilẹ̀ òkèèrè
- Wo iye èèyàn Ukraine àti àjòjì tó ti kú láti ìgbà tí Russia ti gbógun ti Ukriane
- Ta ló ni ₦9bn tí EFCC ká mọ́ ọwọ́ olùṣirò owó àgbà l‘Oyo?
- Ewé sunko fàwọn oníjìbìtì ayélujára mẹ́ta, wò dúkìá tí wọ́n jọwọ fún ìjọba
- Àwọn Oníṣẹ̀ṣe l'Ọ́yọ̀ọ́ ń bèèrè àyájọ́ ìsìnmi láti sààmi ayẹyẹ ọjọ́ ìṣẹ̀ṣe
Nko ni afurasi naa ba ọmọ ọdun mẹjọ ọhun ni ibalopọ.
O ṣalaye pe iya ọmọ ọdun mẹjọ naa lo fi ọrọ ọhun sun ni agọ awọn.
Gẹgẹ bii ohun to sọ, iwa ti afurasi na wu lodi si abala 137, 170 ati 261 ninu iwe ofin iwa ọdaran ipinlẹ Eko ti wọn gbe kalẹ lọdun 2015.
Adajọ ile ẹjọ naa, Patrick Adekomiya, gba beeli afurasi naa pẹlu ẹgbẹrun lọna ọọdunrun naira ati oniduro meji.
O ni ọkan lara awọ oniduro naa gbọdọ jẹ baba to bi afurasi ọhun.
Lẹyin naa lo sun igbẹjọ si ọjọ kejidinlogun, oṣu Kẹta, ọdun 2022, ki igbẹjọ naa le bẹrẹ ni pẹrẹwu.














