You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
NUC Rankings 2021: Púpọ̀ nínú àwọn Fásìtì tó ń gbà owó gọbọi lọ́wọ́ akẹ́kọ̀ọ́ ló fìdí rẹmi nínú ìgbéléwọ̀n wà- NUC
Ninu gbogbo fasiti to wa ni Naijiria,marundinlọgbọn pere ni a ti fòntẹ̀ lu awọn eto ẹkọ tí wọn n se fawọn akẹkoo.
Ohun tí àjọ tó n mojuto eto awọn ile ẹkọ Fasiti Naijiria so di mimọ ree pẹlu igbelewọn ọdun 2021 to se fawọn ile ẹkọ gíga ilẹ naa.
Bẹẹ ni ajọ na fi kun pe awọn eto ẹkọ tàwọn fòntẹ̀ lù láwọn fasiti to ku ko to ida aadọrin ninu ida ọgọrun un.
- Lásìkò ìséde Covid 19, wo bí àwọn olùgbé ìlú yí ṣé n fí fóónù ṣé pàṣípààrọ̀ oúnjẹ
- Inú wa dún pé Oba Oke dá ẹ̀mí Iyabo Oko padà, a gbàgbọ́ pé ìya wa ṣì máa gbádùn pẹ̀lú àdúrà- Omo Iyabo Oko
- Àrà mérìírí! Ìbejí tí a bí ní ọdun 2021 àti 2022 pẹ̀lú ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀dògún láàrin wọn
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó ti wẹ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún àti òṣìṣẹ́ márùn-ún ilé ẹ̀kọ́ Dowen College mọ́
- Ta ni Oloye Lekan Balogun tí àwọn Ìgbìmọ̀ Afọbajẹ Ibadan fẹnukò pé òun ni Olubadan ilẹ̀ Ibadan kàn?
- Afenifere, PDP, Ohaneze sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí Buhari lórí ọ̀rọ̀ tó sọ nípa ètò ààbò
Mẹjọ ninu awọn fasiti ọgọrun le mẹtala tawon àjọ yi se ayẹwo gẹgẹ bí ile iṣẹ iroyin Naijiria The Nation se so ni won6 ko fọwọ́ sí wòrò kan ninu awọn eto eko5 ti wọn n ṣe.
Ninu wọn lati ri "Nigeria Army University, Biu, ni ipinlẹ Borno State ati Air Force Institute of Technology.
Lapapọ fasiti 170 ti ijoba ati aladani lo wa ni Naijiria.
Gẹgẹ bí àjọ NUC ti ṣe sọ ko kankan ninu awọn fasiti 113 tàwọn yẹ wò ti iye ọjọgbọn tó yẹ ki wọn ni pé perepere.
Ninu àtẹ igbelewọn ti ajọ yi ṣe fawọn fasiti bakan náà yunifasiti Ibadan UI lo sọ pe o le tente pẹlu ami 454.5
Fasiti aladani Redeemers University lo n tọ lẹhin pẹlu ami 384.96 ;
Covenant University (368.11 points);
Ladoke Akintoka University, Ogbomoso (315.23 points) ati
Federal University of Technology Akure (264.14 points).
O jẹ iyalẹnu pe ko sí kankan ninu awọn fasiti wọnyi ti orukọ wọn jáde nínú fasiti marundinlọgbọn ti wọn fòntẹ̀ lù gbogbo eto ẹkọ pe o kaju osunwọn eleyii táa mọ sí pé wọn gba "accreditation" lede Gẹẹsi.
Awọn fasiti marundinlọgbọn to wẹ gan kankan nípa gbígbà accreditation yi ni awọn fasiti wọnyi:
Adeleke University, Osun State;
Al-Qalam University, Katsina
Caleb University, Lagos
Chrisland University, Lagos
Crescent University, Ogun
Federal University, Lokoja,
Federal University, Wukari,
Federal University, Kashere.
Ninu wọn la tun ti ri :
Hallmark University, Ogun
Hezekiah University, Imo
Ibrahim Babangida University, Niger
Igbenedion University, Edo
Kano University of Science and Technology, Kano;
Kebbi State University of Science and Technology,
Kogi State University ati
Maitama Sule University, Kano
Awọn to ku ni:
McPherson University, Ogun
Mountain Top University, Ogun
Niger Delta University, Delta
Nigeria Defence Academy;
PAMO University of Medical Science, River
Rivers State University;
Samuel Adegboyega University, Edo
Summit University, Kwara ati
Umaru Musa Yar'Ardua University, Katsina
Àjọ NUC salaye ninu abajade iwadii wọn pe awon akoṣẹmọṣẹ lati ẹka eto awọn fasiti mokanlelaadorin lo se iwadii yi.
Ọgá agba àjọ yi teleri Ọjọgbọn Peter Okebukola lo darí ìkọ naa.
Wọn tẹsiwaju ninu abajade wọn pe púpò awọn fasiti to n gba owó gọbọi lọwọ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ lo fìdí rẹmi ninu igbelewọn náà.
- Ikú d'óróó! Àjálù ikú míì tún ṣe Pásítọ̀ Taiwo, ọkọ Bimbo Odukoya
- Australia, New Zealand, Japan,àwọn orílẹ̀-èdè tó ti ṣáájú Nàìjíríà wọ ọdún 2022
- Àsọtẹ́lẹ̀ 2022 àti ìgbésẹ̀ tí Pásítọ̀ Enoch Adeboye fẹ́ gbé lórí ìdojúkọ Nàìjíríà nìyí
- Ohun tí CAN fi ṣíde ọdún 2022 fún gbogbo ọmọ Nàìjíríà nìyí
- Wo bí àwọn gbajúmọ̀ tí ẹ̀ fẹ́ràn yìí ṣe tẹ̀ẹ́ wọ́nú ọdún 2022 àtí ohun t'Ọ́lọ́hun gbé wọn borí
- 'Àṣírí ọkọ mi tú sími lọ́wọ́, ṣé mo le dáríjì í?'