You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Shehu Sani: Àwọn agbébọn ṣèkọlù àdó olóró sí ojú irin Kaduna sí Abuja, orí ló kó wa yọ!
Sẹnetọ tẹlẹri to ṣoju ẹkun gbungbun Kaduna, Shehu Sani ti kede pe ori lo ko awọn yọ lọwọ ado oloro ninu ọkọ oju irin lọna Kaduna si Abuja.
Shehu Sani to fi iroyin naa lede ni ado oloro to ku lẹyin ti awọn agbesunmọmi ṣekọlu si ọkọ oju irin ni Ọjọọru ni ọkọ ou irin wọn gunle lori.
Lori ẹrọ ayelujara ni Sani ti ni awọn agbesunmọmi naa ṣekọlu ọhun ki awọn to kọja, amọ awọn ado oloro naa ṣi wa ni oju popo naa.
- Wo bí wọ́n ṣe yọ́lẹ̀ gbé Nnamdi Kanu wọ inú ilé ẹjọ́ l'Abuja
- Ìjọba ní kí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ni ṣe àyẹ̀wò ọpọlọ f'áwọn Ọlọ́pàá àti agbófinró
- Wo bí Ooni ti Ile-Ife, Pásítọ̀ Sam Adeyemi, Woli Agba, Falz, Mr Macaroni, Tiwa Savage ṣe ṣe àyájọ́ Endsars!
- Mọ̀ nípa àwọn ọmọ Naijiria tó fẹ́ kí Ísírẹ́lì tẹ́wọ́ gbà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà Júù
- Wo ohun tí Baba Ijesha sọ fún BBC níbi ìgbẹ́jọ́ rẹ̀
- Wo àwọn gbajúmọ̀ míràn yàtọ̀ sí Tiwa Savage tí ọ̀rọ̀ fídíò ìbálòpọ̀ wọn ti bọ́ sí orí ayélujára ...
- 'Fídíò ẹ̀rí táa wò ṣàfihàn ibi tí Baba Ijesha ti ń rán ọmọ Princess létí bí òun ṣe fi ọwọ́ kàn án ní ọmọ ọdún méje'
O fikun un pe awọn agbesunmọmi naa tun dana ibọn bo ''enigine'' ọkọ ati ile epọ ọkọ oju irin naa.
'' Ni Ọjọru, awọn agbesunmọmi ṣekọlu si oju irin Kaduna si Abuja pẹlu ado oloro ti wọn si tun da ibọn bo ọkọ oju irin naa.
''Laarọ oni, mo wa ninu ọkọ oju irin naa ni a tun gunle ado oloro miran, ori lo ko wa yọ lọwọ iku.''