Baba Ijesha: Onímọ̀ nípa ìhùwàsí ọmọdé mú ẹ̀rí tuntun wá sí iléẹjọ́ lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha

Igbẹjọ Baba Ijesha tun tẹsiwaju nílé ẹjọ gíga to n gbọ ẹsun ifipabanilopo niluu Eko.

Ṣaaju ni agbẹjọro fún ìjọba ti kọkọ mu ẹlẹri kan, to jẹ onimọ nipa ihuwasi ọmọde, wa siwaju adájọ Oluwatoyin Taiwo to n gbọ ẹjọ náà.

Ẹlẹri náà, Bisi Àjàyí Kayode sọ níwájú ilé ẹjọ ọhun pé ọmọ tí ọrọ naa kan sọ fún oun lásìkò ifọrọwerọ pe lootọ ni Baba Ijesha fọwọ kan òun nígbà tí òun wa ni ọmọ ọdún méje.

Bisi Ajayi tun ṣàfihàn fidio kan níwájú ilé ẹjọ náà, nibi ti oun ati ọmọ náà ti n sọ ọrọ ọhun.

Bó tilẹ jẹ pe agbẹjọro Baba Ijesha gbìyànjú láti da ẹrí Bisi Àjàyí nu lori pe ko koju oṣuwọn lati fi ọrọ wa ọmọ náà lẹnu wò, ṣugbọn adájọ Oluwatoyin Taiwo gba ẹrí náà wọlé.

Wayi ọ, agbẹjọro ìjọba tun ti mu ẹlẹri miran wa siwaju ile ẹjọ náà.

Ẹlẹri tuntun yii, dokita Makanjuola sọ níwájú ilé ẹjọ náà pé òun lo ṣe ayẹwo ọmọ ti ọrọ kan lati mọ boya lootọ ni Baba Ijesha ti fọwọ kan ri.

Nibi ti ọrọ naa de duro báyìí, adajọ ti wa sun ẹjọ náà sì ọjọ karun un ati ọjọ kẹjọ, oṣù Kọkànlá, ọdún 2021 yìí, gẹgẹ bíi oun ti agbẹjọro Baba Ijesha sọ.

Nínú ìfọrọwánilẹnuwò pẹlu BBC Yorùbá, ọkan lára àwọn agbẹjọro Baba Ijesha, ti Babatunde Ogele n dari wọn sọ pé àwọn ṣi n retí ki ìkọ olupẹjọ mú ẹlẹri mẹta mii wa ko to kan awọn.