You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Ibrahim Elzakzaky: Kí ni àwọn ẹ̀sun tuntun tí ìjọba ìpínlẹ̀ Kaduna tún gbé dìde tako Ibrahim El-zakzaky, olórí ìjọ Mùsùlùmí Shiite ní Nàìjíríà?
Lẹyin ọjọ meji ti ile ẹjọ giga kan ni ipinlẹ Kaduna yọ ọrọ ẹjọ lọrun aṣiwaju ijọ Islamic Movement of Nigeria, IMN Sheikh Ibrahim El-zakzaky, ijọba ipinlẹ Kaduna tun ti n gbe awọn ẹsun miran dide.
Ẹsun ẹjọ meje ọtọọtọ miran ni wọn tun gbe dide tako Sheikh El-zakzaky niwaju ile ẹjọ giga apapọ kan.
Olupẹjọ agba fun ijọba ipinlẹ Kaduna, Daris Bayero ṣalaye fun ileeṣẹ iroyin Channels pe lara awọn ẹsun tuntun ti wọn fi kan olori ẹsin naa ni igbesunmọmi, kikọju ija si ijọba ipinlẹ naa ati ijọba apapọ.
- 'Lábẹ́ òfin àjọ ECOWAS, kó ṣééṣe kí Benin Republic jọ́wọ́ Sunday Igboho fún Nàìjíríà'
- Àwọn ohun mẹ́rin tó yẹ kí ẹ ko mọ nípa Ramoni Igbalode tí gbogbo ayé ń pè ní Hushpuppi
- Ikú Tope AjogbaJesu, ohun tí a mọ̀ nípa ohun tó ṣokùnfà ikú rẹ̀ nìyí
- 'Ẹ yọ Ọgá Ọlọ́pàá Abba Kyari tí US fẹ̀sùn kàn lórí ọ̀rọ̀ Hushpuppi kúrò nípò kíá!'
O ni awọn kan lara ẹsun tuntun ti wọn fi n kan an jẹyọ lati ara awọn ohun to ti n ṣe ṣiwaju ọdun 20215.
Amofin Bayero ni o di dandan ki ile ẹjọ gbe aṣẹ tuntun fun mimu Sheikh El-zakzaky kalẹ lati lee wa dahun si awọn ẹsun naa.
Lati nnkan bii ọdun mẹrin bayii ni olori ijọ ẹsin musulumi Shiite lorilẹede Naijiria naa ti n jẹjọ pẹlu iyawo rẹ Zeenat lori awọn ẹsun bii dida alaafia ilu ru, pipejọpọ lọna ti ko tọ ati awọn ẹsun mẹjọ miran to da le ipaniyan.
Amọṣa ni Ọjọru, ọjọ kejidinlọgbọn ọdun 2021 ni Onidajọ Gideon Kurada dajọ pe ẹsun ti wọn fi kan oun ati iyawo rẹ ko lẹsẹ nlẹ.