You’re viewing a text-only version of this website that uses less data. View the main version of the website including all images and videos.
Lagos-Ibadan Expressway Fire: Kíló fa iná tó sọ ní òpópónà Ibadan sí Eko tó gbẹ̀mí ènìyàn tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ sì jóná?
Ijamba ina sọ ni opopona Ibadan si Eko ni agbegbe Ọgere ni owurọ Ọjọ Iṣẹgun, to si mu ẹmi eniyan meji lọ pẹlu ọpọlọpọ ọkọ to jọna ninu iṣẹlẹ naa.
Adari ileeṣẹ irinna oju popo nipinlẹ Ogun, Arakunrin Ahmed Umar to fi idi ọrọ naa mulẹ ni nkan bi aago mẹfa aarọ oni lo ṣẹlẹ.
Umar ni iwaju ibudokọ Romona ti awọn ọkọ nla ni Ogere ni iṣẹlẹ naa ti waye.
O ni ijanu ọkọ to gbe bẹntirolu lo da iṣẹ silẹ, to si lọ kọlu ọkọ miran to wa loju ọna , eleyii to fa ija to si mu ẹmi lọ.
- 'Kò sí ẹni tó lè ní kí a má wá sí Èkó, iwọ́de òní pẹ̀lẹ́ kùtù la fẹ́ ṣe'
- Ohun tó dára fún ètò ọ̀rọ̀ ajé wá ni láti yá owó fún ṣíṣe ojú pópó wá - Fashola
- Gómìnà ṣàbẹ̀wò sí àwọn tí ọlọ́pàá yìnbon lù l'Enugu, Ọ̀gá ọlọ́pàá ní ìwádìí gbọdọ̀ wáyé kíákíá
- Father's Day fa gbas-gbos láàrin Mercy Aigbe àti ọkọ rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Gentry, ọkọ́ ní òun le tú àwọn àṣírí ìwà nọ̀bì rẹ̀ síta
- Ìgbẹ́jọ́ Kemisola Ogunniyi kò wáyé lóní, ó tún dọ̀la, ṣùgbọ́n... - Agbẹjọ́rọ̀
Bakan naa lo fikun pe sunkẹrẹ-fakẹrẹ ọkọ to ṣẹlẹ laarọ nitori oju ọna ti wọn n tunṣe nibẹ, to si mu ki wọn ṣi oju ọna kan ṣoṣo to sokunfa iṣẹlẹ naa.
''Ina naa pọ gidigan an ni ti a ko tii le ṣọ iye ọkọ to jona ninu iṣẹlẹ naa.
Ọkan lara awọn ti iṣẹlẹ naa ṣoju rẹ ni awọn awakọ tirela nla mejeeji to kolu ara wọn to si fa ijamba ina naa ni ẹmi wọn ti lọ si iṣẹlẹ naa.
Lọwọlọwọ bayii, awọn ẹsọ alaabo, panapana ti wa nibẹ lati ri pe wọn ri ojutu ina to sọ naa.
Bakan naa ni ọkọ kankan ko le e lọ siwaju lasiko yii, nise ni wọn duro si oju kan naa nitori awọn eniyan si n woye wi pe o ṣeeṣe ki awọn ọkọ nla miran to gbe afẹfẹ gaasi ṣi le jona.