Water Scarcity in Ogun Community: Àwa àtàwọn máàlù la jọ ń du mu omi yìí láti mu

Àkọlé fídíò, Bí mo ṣe mu omi yiìí láàrọ́ yìí rèé torí mi ò ní N50 owó álọ́ọ̀mù, a sì ń dìbò lọ́dọọdún o- Olúgbé Yewa ìpínlẹ̀ Ogun

"Bí omi yii ti a n mu ṣe ri latigba ti alaye ti daye ti a si n mu u niyii".

Ni ilu kan, Igbooro/Orobiyi ni agbegbe ijọba ibilẹ iha Ariwa Yewa, ipinlẹ Ogun ni omi idọti yii ti n gbayii gẹgẹ bi eyi to ṣi mọju ti wọn n bu mu, bu wẹ, bu dana jẹun.

Omi idọti ni ilu Igborọ

Pẹlu bi ajọ isọkan agbaye UN ṣe n pariwo fun ipese omi to mọ gaara to, ilu yii ko ni orisun omi to dara fun mimu rara.

Omi idọti ni ilu Igborọ

Awọn ara ilu Igorọ ni omi abata ati ẹrọfọ ni awọn n ri pọn lati lo.

Janet Opeisa to jẹ ọkan lara awọn olugbe ilu Igborọ mu BBC Yoruba rin irinajo ti kii ṣe keremi lọ sinu ira ti wọn ti n pọn omi.

Omi idọti ni ilu Igborọ

"A o tun ni ibi kankan mọ o, aa wa gbe e kalẹ, aa joko aa maa yọ ọ. Ki la fẹ ri ninu eleyii?".

O ni to ba ṣe pe awọn Fulani darandaran ti yọju si ilu wọn pẹlu awọn maalu wọn ni, omi yii kan naa lawọn n jọ n mu.

"Táa bá ní kí àwọn Fulani àti máàlù wọn má wẹ sínú omí yìí, wọn á ní orí wa ti dàrú".

Omi idọti ni ilu Igborọ

Ẹwẹ, tori eyi, BBC Yoruba kan si ijọba ipinlẹ Ogun ti wọn si fesi pe awọn ni ileeṣẹ to n mojuto eyi ti wọn si ti gbẹ kọnga si aimoye ilu...

Kí wá ni àwọn ara ilu Igborọ ni Yewa fi ṣe ori ti mudunmudun yii ko tii kan wọn latigba ti alalye ti daye gẹ́gẹ́ bi wọ́n sọ.